A mú àwọn ọmọ ’Isrọ̄‘īl la agbami odò já. Nígbà náà, wọ́n kọjá lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn kan tí wọ́n dúró ti àwọn òrìṣà wọn. Wọ́n sì wí pé: “Mūsā, ṣe òrìṣà kan fún wa, gẹ́gẹ́ bí àwọn (wọ̀nyí) ṣe ní àwọn òrìṣà kan.” (Ànábì) Mūsā sọ pé: “Dájúdájú ẹ̀yin ni ìjọ aláìmọ̀kan.
____________________
Nínú ẹ̀rí t’ó ń fi rinlẹ̀ pé iṣẹ́-ìyanu kì í sábà mú ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ àwọn ènìyàn di onígbàgbọ́ òdodo ni āyah yìí wa. Ǹjẹ́ pẹ̀lú àwọn àmì ìyanu tí àwọn ọmọ ’Isrọ’īl ti f’ojú ara wọn rí bẹ̀rẹ̀ láti ibi tí wọ́n ti ń bọ̀ títí dé ibi tí wọ́n dé yìí, ṣé ó tún yẹ kí wọ́n máa bèèrè fún òrìṣà kan kan? Ṣé òrìṣà l’ó ti ń ràn wọ́n lọ́wọ́ bọ̀ ni tàbí Allāhu Alágbára? Nítorí náà, àwọn aláìmoore àti aláìníkan-ánṣe l’ó máa ń wá iṣẹ́ ìyanu kiri. Ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun ti tó fún ẹni t’ó níkan-ánṣe. Ẹ wo sūrah Yūnus; 10 :96-97.


الصفحة التالية
Icon