Yálà o tọrọ àforíjìn fún wọ́n tàbí o ò tọrọ àforíjìn fún wọn – kódà kí o tọrọ àforíjìn fún wọn nígbà ààdọ́rin – Allāhu kò níí foríjìn wọ́n. Ìyẹn nítorí pé dájúdájú wọ́n ṣàì gbàgbọ́ nínú Allāhu àti Òjísẹ́ Rẹ̀. Allāhu kò níí fi ọ̀nà mọ ìjọ òbìlẹ̀jẹ́.
____________________
Pẹ̀lú gbólóhùn yìí, àwọn kò-gbédè-ó-gbékèé nínú àwọn kristiẹni lérò pé Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kò lè tọrọ àforíjìn lọ́dọ̀ Allāhu fún àwa ọmọlẹ́yìn rẹ̀, kí Allāhu sì foríjìn wá. Ọ̀rọ̀ kò sì rí bẹ́ẹ̀ rárá. Àmọ́ ohun tí ń bẹ nínú āyah yìí ni pé, kò sí àforíjìn Allāhu fún òkú àwọn ṣọ̀bẹ-ṣèlu mùsùlùmí, gẹ́gẹ́ bí kò ṣe sí àforíjìn Allāhu fún òkú àwọn aláìgbàgbọ́ àti òkú àwọn ọ̀ṣẹbọ, ẹni yòówù ó bá wọn tọrọ àforíjìn. Nípa ti òkú àwọn aláìgbàgbọ́, ẹ wo āyah 84 níwájú. Nípa ti òkú àwọn ṣọ̀bẹ-ṣèlu mùsùlùmí, ẹ wo sūrah al-Munāfiƙūn; 63:6. Bákan náà, nípa ti òkú àwọn ọ̀ṣẹbọ, ẹ wo sūrah an-Nisā’; 4:48 àti 116 àti sūrah at-Taobah; 9:113. Bákàn náà, bíbá tí Allāhu ni kí àwọn mùsùlùmí lọ bá Ànábí (sollalāhu 'alayhi wa sallam) láti lè bá wọn tọrọ àforíjìn, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà nínú Sūrah an-Nisā’; 4:64, ìyẹn náà ti wá sópin nípasẹ̀ ikú Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Ọ̀wọ́ ìgbà tí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ń bẹ nílé ayé ṣíwájú kí ó tó kú nìkan ni ó lè bá ẹnikẹ́ni nínú àwọn mùsùlùmí tọrọ àforíjìn lọ́dọ̀ Allāhu (subhānahu wa ta'ālā). Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì máa foríjìn ín. Àmọ́, Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kò lè ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́ lẹ́yìn ikú rẹ̀ nínú sàréè rẹ̀. Ó sì di Ọjọ́ Àjíǹde kí Ànábì wa tó lè bá wa ṣ’ìpẹ̀ àṣegbà níwájú Allāhu (subhānahu wa ta'ālā). Nítorí náà, ìṣẹbọ sí Allāhu ni fún ẹnikẹ́ni láti lọ bá Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ní ìdí sàréè rẹ̀ fún títọrọ n̄ǹkan lọ́dọ̀ rẹ̀.