Nítorí náà, wọ́n sọ pé: "Allāhu la gbáralé. Olúwa wa, má ṣe wá ní àdánwò fún ìjọ alábòsí.
____________________
Ìyẹn ni pé, kí Allāhu má ṣe fi ọ̀tá ẹ̀sìn wa borí wa. Tàbí àdánwò t’ó máa kàn wá tí àwọn ọ̀tá ẹ̀sìn wa yóò fi lérò pé a kì í ṣe ẹni Allāhu, kí Allāhu má ṣe fi kàn wá. Ìdí ni pé, àdánwò tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ń fi kan ẹ̀dá nílé ayé, kò níí ṣe pọ̀ pẹ̀lú jíjẹ́ ẹni Ọlọ́hun tàbí àìjẹ́ ẹni Ọlọ́hun nítorí pé, Aṣèyí-Ó-wùú ni Allāhu. Bí àpẹẹrẹ, ẹ wo àdánwò àìlera tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) fi kan Ànábì ’Ayyūb ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām), tòhun ti bí ó ṣe jẹ́ Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun. Ànábì Yūsuf ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) di ẹni tí wọ́n fi sínú ẹ̀wọ̀n lórí ẹ̀sùn ìparọ́-sìná-mọ́ni, tòhun ti bí ó ṣe jẹ́ Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun. Nítorí náà, mùsùlùmí bùkátà sí ìrawọ́rasẹ̀ sí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā).


الصفحة التالية
Icon