Ẹ má ṣe pe àwọn tí wọ́n ń pa sí ojú-ogun ẹ̀sìn Allāhu ní òkú (ìyà), àmọ́ alààyè (ẹni ìkẹ́) ni wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fura.
____________________
A bi ‘Abdullāh léèrè nípa āyah yìí, ‘Abdullāh sọ pé, àwa kúkú bi Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) léèrè nípa èyí, ó sì sọ pé: “Ẹ̀mí àwọn tí wọ́n kú sí ojú ogun ẹ̀sìn ’Islām yóò máa bẹ nínú agbẹ̀du ẹyẹ aláwọ̀ ewéko. Àwọn ẹyẹ náà ní àtùpà tí wọ́n gbékọ́ fún wọn s’ára Ìtẹ́-ọlá ti Allāhu. Àwọn ẹyẹ náà ń jẹ kiri síbi tí wọ́n bá fẹ́ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra. Lẹ́yìn náà, àwọn ẹyẹ náà yóò fara pamọ́ sídìí àwọn àtùpà wọ̀nyí. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣíjú wò wọ́n, Ó sì sọ pé: “Ẹ̀ ń fẹ́ n̄ǹkan bí? Wọ́n sọ pé: “Kí ni n̄ǹkan tí a tún ń fẹ́? Àwa tí à ń jẹ kiri síbi tí a fẹ́ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.” Allāhu ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú wọn ní ẹ̀ẹ̀ mẹta. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí i pé Wọn kò fi àwọn sílẹ̀ nípa bíbi wọ́n pé kí ni n̄ǹkan tí wọ́n tún ń fẹ́, wọ́n bá sọ pé: "Olúwa, a fẹ́ kí O dá ẹ̀mí wa padà sínú ara wa, kí wọ́n lè tún wa pa ní ẹ̀ẹ̀ kan sí i sí ojú ogun ẹ̀sìn Rẹ." Nígbà tí Allāhu rí i pé wọn kò ní bùkátà kan mọ́ (Allāhu, Onímọ̀ nípa ohun gbogbo sì ti mọ̀ ṣíwájú kí Ó tó bi wọ́n léèrè), Wọ́n fi àwọn ẹ̀yẹ̀ náà sílẹ̀ sínú Ọgbà Ìdẹ̀ra. (Bukọ̄riy; al-Jihād was-saer: 3500). Irúfẹ́ āyah yìí wà ní sūrah āli ‘Imrọ̄n; 3:169. Kókó tí àwọn āyah wọ̀nyí fi rinlẹ̀ sì ti jẹyọ nínú hadīth yẹn, ìyẹn ni pé, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) dùn-ún gbè níjà t’ó bẹ́ẹ̀ gẹ́ t’ó fi jẹ́ pé àwọn tí wọ́n bá kú fún Un, àwọn ni wọ́n kú ikú tí ó lápọ̀n-ọ́nlé jùlọ, tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ tí wọn yóò fi máa bẹ nínú Ọgbà Ìdẹ́rà ní àwòrán ẹyẹ aláwọ̀ ewéko ṣíwájú Ọjọ́ àjíǹde. Àti pé kò sí àǹfààní fún òkú kan kan láti padà sílé ayé mọ́. Nítorí náà, kò sí àkúdàáyà tàbí àṣẹ̀yìnwáyé kan níbikíbi bí kò ṣe ète àlùpàídà tí àwọn èṣù àlùjànnú ń dá. Àwọn èṣù àlùjànnú l’ó ń gbé àwòrán ọmọnìyàn wọ̀ láti fi ba ìgbàgbọ́ wọn jẹ́. Ẹ wo sūrah al-Mu’minūn; 23:99-100 àti sūrah Yāsīn; 36:48-54.


الصفحة التالية
Icon