A ò rán ẹnì kan ní iṣẹ́-òjíṣẹ́ ṣíwájú rẹ àfi àwọn ọkùnrin tí À ń fi ìmísí ránṣẹ́ sí nínú àwọn ará ìlú. Ṣé wọn kò rìn kiri lórí ilẹ̀ kí wọ́n wo bí ìkángun àwọn t’ó ṣíwájú wọn ṣe rí? Dájúdájú Ilé ìkẹ́yìn lóore jùlọ fún àwọn t’ó bẹ̀rù (Allāhu). Ṣé ẹ ò ṣe làákàyè ni?
____________________
Lóde òní yìí, à ń rí àwọn obìnrin kan tí wọ́n ń sọra wọn di aṣíwájú ẹlẹ́sìn nínú ìjọ ’Islām àti nínú ìjọ Kristiẹniti. Wọ́n sì ń sọ pé Ọlọ́hun l’Ó fi iṣẹ́ ẹ̀sìn rán àwọn níṣẹ́. Wọ́n ń sọra wọn di ànábì Ọlọ́hun àti òjíṣẹ́ Rẹ̀. Āyah yìí ti já wọn nírọ́. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ti fi rinlẹ̀ pé, Òun kò fi iṣẹ́ ìmísí rán obìnrin kan kan rí. Ẹ jìnnà sí irú àwọn obìnrin abẹ̀sìnjẹ́ náà. Kíyè sí i! Bí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe ṣa Mọryam, ìyá Ànábì ‘Īsā lẹ́ṣà tó, kò fi iṣẹ́ ìmísí rán an sí ẹnikẹ́ni.