A ò rán ẹnì kan ní iṣẹ́-òjíṣẹ́ ṣíwájú rẹ àfi àwọn ọkùnrin tí À ń fi ìmísí ránṣẹ́ sí. Nítorí náà, ẹ bèèrè lọ́dọ̀ àwọn oníràn-ántí tí ẹ̀yin kò bá mọ̀.
____________________
Nínú al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé, àyè méjì péré ni Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ti pe àwọn kan ní “ahlu-ththikr” (ìtúmọ̀ “àwọn oníràn-ántí / àwọn tí A sọ ìrántí kalẹ̀ fún). Àyè kìíní ni sūrah an-Nahl; 16:43. Àyè kejì ni sūrah al-‘Anbiyā’; 21:7. Àwọn sūfī sì ń lérò pé àwọn ni “ahlu-ththikr”. Àti pé àwọn gan-an ni Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ń tọ́ka sí nínú àwọn āyah méjèèjì náà.
Èsì: Ohun tí wọ́n ń sọ yìí kì í ṣe òtítọ́ páàpáà. Èyí tí í ṣe òdodo ọ̀rọ̀ ni pé, àwọn onímọ̀ nípa at-Taorāt àti al-’Injīl ni Allāhu ń tọ́ka sí, kì í ṣe àwọn sūfī. Ìdí ni pé, okùnfà āyah méjèèjì yìí ni pé, Allāhu fi fọ èsì sí ọ̀rọ̀ àwọn ọ̀ṣẹbọ tí wọ́n ń sọ pé mọlaika ni Allāhu máa ń fi iṣẹ́ Òjíṣẹ́ rán, kì í ṣe ènìyàn. Àwọn ọ̀ṣẹbọ wọ̀nyẹn sì ni Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ń pàṣẹ fún pé kí wọ́n lọ bèèrè wò lọ́dọ̀ àwọn onímọ̀ nípa tíra ìṣáájú bóyá ní òdodo ni Allāhu ti fi iṣẹ́ Òjíṣẹ́ rán mọlāika kan rí sí àwọn ènìyàn, tí yó sì máa gbé láààrin wọn ṣíwájú Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Àtakò àwọn ọ̀ṣẹbọ wọ̀nyí l’ó tún bí ìsọ̀kalẹ̀ sūrah Yūnus; 10:2. Ẹ tún wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah Yūsuf 12:109.


الصفحة التالية
Icon