Sọ pé: “Dájúdájú tí àwọn ènìyàn àti àlùjànnú bá para pọ̀ láti mú irú al-Ƙur’ān yìí wá, wọn kò lè mú irú rẹ̀ wá, apá kan wọn ìbáà jẹ́ olùrànlọ́wọ́ fún apá kan."
____________________
Kíyè sí i, āyah yìí kò túmọ̀ sí pé àwọn olórí kunkun ènìyàn kan kò níí gbìyànjú láti hun ọ̀rọ̀ jọ láti pè é ní Kur’ān. Ṣebí àwọn kan mú àwọn àròsọ kan wá, wọ́n sì ń pè é ní “Bíbélì”. Àmọ́ èyíkéyìí àròsọ náà yóò máa jẹ́ ọ̀rọ̀ tí kò níí ní ìbùkún, kò sì níí ti ipasẹ̀ mọlāika wá, Ó tún máa jẹ́ ọ̀rọ̀ tí àwọn mùsùlùmí kó níí tẹ́wọ́ gbà. Kódà ọ̀rọ̀ àdáhun bẹ́ẹ̀ máa kún fún ìtakora, irọ́, ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ ẹlẹ́mìí Èṣù.


الصفحة التالية
Icon