Báyẹn ni A ṣe jẹ́ kí àwọn ènìyàn rí wọn nítorí kí wọ́n lè mọ̀ pé dájúdájú àdéhùn Allāhu ni òdodo. Àti pé dájúdájú Àkókò náà kò sí iyèméjì nínú rẹ̀. Rántí (nígbà tí àwọn ènìyàn) ń ṣe àríyànjiyàn láààrin ara wọn nípa ọ̀rọ̀ wọn. Wọ́n sọ pé: "Ẹ mọ ilé kan lé wọn lórí. Olúwa wọn nímọ̀ jùlọ nípa wọn." Àwọn t’ó borí lórí ọ̀rọ̀ wọn sì wí pé: “Dájúdájú a máa sọ orí àpáta wọn di mọ́sálásí.”
____________________
Láti ọ̀dọ̀ ‘Ā’iṣah (r.ah), ó sọ pé, Òjíṣẹ́ Allāhu (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sọ lórí ìdùbúlẹ̀ àìsàn tí ó kú sórí rẹ̀ pé: “Ibi dandan Allāhu ń bẹ lórí àwọn yẹhudi àti nasara (nítorí pé) wọ́n sọ sàréè àwọn Ànábì di ilé ìjọ́sìn.” ‘Ā’iṣah sọ pé: “Tí kì í bá ṣe nítorí èyí ni, wọn ìbá ṣe àfihàn ojú sàréè rẹ̀ ṣùgbọ́n dájúdájú ẹ̀rù ń bà wọ́n pé kí wọ́n má sọ sàréè rẹ̀ di mọ́sálásí. (Muslim) Kíyè sí i, ní ìpìlẹ̀ wọ́n sin òkú Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sí ibi tí ó kú sí nínú yàrá ìyá wa, ‘Ā’iṣah (r.ah). Ní ọjọ́ náà sì nìyí wọ́n kọ́ ilé Ànábì papọ̀ mọ́ mọ́sálásí rẹ̀ ni. Ilé rẹ̀ sì bọ́ sí ọwọ́ iwájú mọ́sálásí. Àmọ́ nígbẹ̀yìn-gbẹ́yín fífẹ̀ tí wọ́n padà fẹ mọ́sálásí rẹ̀ lójú sí ọ̀tún, òsì, ẹ̀yìn àti iwájú, wọn kò sì fẹ́ wú òkú Ànábì àti òkú Abu-Bakr àti òkú ‘Umar jáde kúrò nínú sàréè, èyí l’ó ṣokùnfà tí ilé náà fi bọ́ sínú mọ́sálásí. Irú ìṣẹ̀lẹ̀ yìí kò gbọdọ̀ ṣẹlẹ̀ sí mọ́sálásí, ní ìbámu sí hadīth ìya wa ‘Ā’iṣah tí a mú wá ṣíwájú. Èyí tí ó sì ṣẹlẹ̀ sí mọ́sálásì Òjísẹ́ yìí náà (sollalāhu 'alayhi wa sallam) yóò padà ní àtúnṣe lọ́jọ́ iwájú ’in ṣā Allāhu, nítorí pé èèwọ̀ ni kí sàréè bọ́ sínú mọ́sálásí láì la àyàfi lọ!


الصفحة التالية
Icon