Àyàfi (kí o fi kún un pé) "tí Allāhu bá fẹ́." Ṣe ìrántí Olúwa rẹ nígbà tí o bá gbàgbé (láti sọ bẹ́ẹ̀ lásìkò náà). Kí o sì sọ (fún wọn) pé: “Ó rọrùn kí Olúwa mi tọ́ mi sọ́nà pẹ̀lú èyí tí ó súnmọ́ jù èyí lọ ní ìmọ̀nà (fún yín).”
____________________
Okùnfà āyah yìí ni pé, nígbà tí àwọn yẹhudi wá bi Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) léèrè nípa ọ̀rọ̀ àwọn ará inú ihò àpáta pẹ̀lú èròǹgbà wọn pé tí ó bá jẹ́ Ànábì Ọlọ́hun ní ti òdodo, ó yẹ kí ó nímọ̀ nípa wọn, Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sì sọ fún wọn pé kí wọ́n wá gbọ́ ìtàn wọn ní ọjọ́ kejì pẹ̀lú èròǹgbà pé Allāhu á ti fi ìmísí nípa wọn ránṣẹ́ sí òun. Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kò sì sọ fún àwọn yẹhudi náà pé “tí Allāhu bá fẹ́.” Àmọ́ àì sọ bẹ́ẹ̀ rẹ̀ jẹ́ kí ọjọ́ àdéhùn t’ó ṣe fún wọn yẹ̀. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì fi ìṣẹ̀lẹ̀ náà kọ́ Ànábì Rẹ̀ (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ní ẹ̀kọ́ pé, ó yẹ kí ó fi kún un fún wọn pé “tí Allāhu bá fẹ́.” Lẹ́yìn náà, ìmísí nípa àwọn ará inú ihò àpáta dé. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì tún jẹ́ kí ó di mímọ̀ fún Ànábì Rẹ̀ (sollalāhu 'alayhi wa sallam) pé, àwọn ìtàn ìmọ̀nà mìíràn wà tó lè mú kí àwọn yẹhudi wọ̀nyẹn mọ̀ pé dájúdájú Òjíṣẹ́ Allāhu ní í ṣe. Tí wọ́n bá ṣetán láti tẹ̀lé ìmọ̀nà tí Ànábì mú wá, Allāhu tún lè sọ àwọn ìtàn t’ó lọ́jọ́ lórí ju ti àwọn ará inú ihò àpáta, t’ó sì tún lágbára jùlọ láti fún àwọn ọkàn ní ìmọ̀nà. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì kúkú ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ ayérayé, àwọn ọ̀rọ̀ ìgbà-àwá-sẹ̀ bíi ìtàn ìṣẹ̀dá ayé àti ọ̀run, ìtàn àwọn Ànábì àti àwọn Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun t’ó ti ré kọjá lọ tí kò sí déètì rẹ̀ lọ́wọ́ ẹnì kan kan. Àmọ́ sá, olórí-kunkun ni àwọn yẹhudi; wọ́n gbọ àwọn ìyáláàyá ìtàn òdodo náà, wọ́n sì gbúnrí láti padà sínú ’Islām.


الصفحة التالية
Icon