(Ẹ rántí) ẹlẹ́ja, nígbà tí ó bá ìbínú lọ, ó sì lérò pé A ò níí gbá òun mú. Ó sì pe (Olúwa rẹ̀) nínú àwọn òkùnkùn (inú ẹja) pé: "Kò sí ọlọ́hun tí ìjọ́sìn tọ́ sí àfi Ìwọ (Allāhu). Mímọ́ ni fún Ọ. Dájúdájú èmi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn alábòsí."
____________________
Kíyè sí i, ohun tí Ànábì Yūnus ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) kà kún àbòsí nínú àdúà rẹ̀ yìí kì í ṣe ìjàǹbá nítorí pé, kò sí Ànábì t’ó jẹ́ oníjàǹbá. Àmọ́ ohun tí ó ṣe ni pé, ó kánjú kúrò láààrin àwọn ènìyàn rẹ̀ tí wọ́n tọrọ ìyà, tí ìyà náà sì fẹ́ sọ̀kalẹ̀ lé wọn lórí. Nítorí kí ìyà má baà kó òun náà sínú l’ó fi kánjú yẹra fún wọn. Ó sì yẹ kí ó ṣe bẹ́ẹ̀. Àmọ́ ohun tí ó yẹ jùlọ fún un ni pé, kí ó gba àṣẹ láti ṣe bẹ́ẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Allāhu (subhānahu wa ta'ālā). Ṣebí Allāhu t’ó rán an níṣẹ́, Ó ń gbọ́ ọ. Ó sì ń rí i.


الصفحة التالية
Icon