Ẹ̀ẹ̀ karùn-ún sì ni pé kí ìbínú Allāhu máa bá òun, tí ọkọ òun bá wà nínú àwọn olódodo.
____________________
Tí abilékọ bá bí ọmọ, àmọ́ tí ọkọ rẹ̀ sọ pé òun kọ́ ni òun ni ọmọ náà, tí ìyàwó sì takú pé ọkọ òun l’ó ni ọmọ náà, ìgbéyàwó náà máa túká pẹ̀lú ìṣẹ́bi láààrin tọkọ tìyàwo náà lórí ìlànà t’ó wà nínú āyah 6 sí āyah 9. Lẹ́yìn ìṣẹ́bi náà, ọmọ náà yóò máa bá ìyá rẹ̀ lọ. Ìkíní kejì kò sì lè di tọkọ tìyàwó mọ́. Nítorí náà, kí ẹnì kọ̀ọ̀kan máa ṣọ́ abẹ́ rẹ̀ àti ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ níbi fífi ẹ̀sùn zinā kan ẹnì kejì rẹ̀.


الصفحة التالية
Icon