ní ìṣaájú. Ìmọ̀nà sì ni fún àwọn ènìyàn.1 Ó tún sọ ọ̀rọ̀-ìpínyà (ọ̀rọ̀ t’ó ń ṣèpínyà láààrin òdodo àti irọ́) kalẹ̀.2 Dájúdájú àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́ nínú àwọn āyah Allāhu, ìyà t’ó le ń bẹ fún wọn. Allāhu sì ni Alágbára, Olùgbẹ̀san.
____________________
1 Gbólóhùn yìí níí ṣepọ̀ pẹ̀lú ìjọ àti àsìkò. Ìyẹn ni pé, ìjọ ’Isrọ’īl nìkan ni tírà Taorāh àti ’Injīl jẹ́ ìmọ̀nà fún. Ìjọ Ànábì Mūsā ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) l’ó ni Taorāh. Ìjọ Ànábì ‘Īsā ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) l’ó sì ni ’Injīl. Àmọ́ lẹ́yìn tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sọ al-Ƙur’ān kalẹ̀ fún Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam), ẹni tí Allāhu ṣe gbogbo ayé ní ìjọ rẹ̀, tí ó sì jẹ́ Ànábì ìkẹ́yìn (sollalāhu 'alayhi wa sallam), kò lẹ́tọ̀ọ́ fún ẹnikẹ́ni mọ́ láti tẹ̀lé Taorāh àti ’Injīl kan kan mọ́ àyàfi al-Ƙur’ān, gẹ́gẹ́ bí kò ṣe lẹ́tọ̀ọ́ láti tẹ̀lé Ànábì Mūsā àti Ànábì ‘Īsā lásìkò yìí àfi Ànábì ìgbà yìí, Ànábì Muhammad. Kò wulẹ̀ sí ojúlówọ́ Taorāh àti ’Injīl ní àsìkò yìí mọ́ ní ìbámu sí sūrah al-Baƙọrah; 2:75, 79 àti sūrah al-Mọ̄’idah; 5:13. Nínú Sọhīh Muslim, láti ọ̀dọ̀ ’Abū Huraerah, láti ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ Allāhu (sollalāhu 'alayhi wa sallam), dájúdájú ó sọ pé: “Èmí fi Ẹni tí ẹ̀mí mi wà ní ọwọ́ Rẹ̀ búra; ẹnì kan nínú ìjọ yìí, yẹ̀húdí àti kristiẹni, kò níí gbọ́ nípa mi, lẹ́yìn náà kí ó kú láì gba ohun tí Wọ́n fi rán mi níṣẹ́ gbọ́, àfi kí ó wà nínú èrò Iná.” Bákàn náà, nínú tírà musnad ’Ahmọd àti musọnnaf ‘Abdur-Razāƙ, láti ọ̀dọ̀ ‘Abdullāh bun Thābit (rọdiyallāhu 'anhu), Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sọ pé: “Tí ó bá jẹ́ pé Ànábì Mūsā ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) di ẹni tí ó máa wà láàrin yín, lẹ́yìn náà tí ẹ bá tẹ̀lé e, tí ẹ sì pa mí tì, ẹ̀yin ìbá ṣìnà.”
2 Fún àlàyé lórí Furƙọ̄n, ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:53.


الصفحة التالية
Icon