Nítorí náà, àwọn mọlāika pè é nígbà tí ó ń kírun lọ́wọ́ nínú ilé ìjọ́sìn, (wọ́n sọ pé): "Dájúdájú Allāhu ń fún ọ ní ìró ìdùnnú nípa (bíbí) Yahyā. Ó máa fi òdodo rinlẹ̀ nípa ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ Allāhu. (Ó máa jẹ́) aṣíwájú, tí kò sì níí súnmọ́ obìnrin. (Ó máa jẹ́) Ànábì. Ó sì wà nínú àwọn ẹni rere."
____________________
"Ọ̀rọ̀ kan” láti ọ̀dọ̀ Allāhu" ni “Jẹ́ bẹ́ẹ̀” tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) fi ṣẹ̀dá ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) gẹ́gẹ́ bí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe fi rinlẹ̀ nínú sūrah yìí kan náà, āyah 59. Ẹ tún wo sūrah an-Nisā’; 4:171.


الصفحة التالية
Icon