(Ẹ rántí) nígbà tí àwọn mọlāika sọ pé: "Mọryam, dájúdájú Allāhu ń fún ọ ní ìró ìdùnnú (nípa dídá ẹ̀dá kan pẹ̀lú) ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ Rẹ̀. Orúkọ rẹ̀ ni Mọsīh ‘Īsā ọmọ Mọryam. Abiyì ni ní ayé àti ní ọ̀run. Ó sì wà lára alásùn-únmọ́ (Allāhu).
____________________
Àwọn kristiẹni lèrò pé sūrah āli ‘Imrọ̄n; 3:45 tako sūrah Mọryam; 19:17 nípa pé “mọlā’ikah” jẹ́ “ọ̀pọ̀” nínú āyah àkọ́kọ́, ó sì jẹ́ ẹyọ “mọlak” nínú āyah kejì.
Èsì: Èyí jẹ́ “ìtakora tófẹ́jọbẹ́ẹ̀”, kì í ṣe “ìtakora tóríbẹ́ẹ̀”. Àlàyé rẹ̀ nìyí, nínú āyah ti āli ‘Imrọ̄n, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ń sọ nípa bí àwọn mọlā’ikah ṣe wá sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa bíbi ‘Īsā ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Àwọn mọlāika t’ó wá sọ àsọtẹ́lẹ̀ náà ju ẹyọ kan lọ. Ìdí nìyí tí “mọlā’ikah” fi jẹ́ ọ̀pọ̀ nínú āyah yẹn. Àmọ́ nínú āyah ti Mọryam, ẹyọ mọlāika kan péré ni Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) fi “ẹ̀mí” ‘Īsā rán níṣẹ́ sí Mọryam. Ìdí nìyí tí ó fi jẹ́ “mọlak” ẹyọ fún mọlā’ikah. Pẹ̀lú àlàyé yìí, ọ̀tọ̀ ni àsìkò àsọtẹ́lẹ̀ fún Mọryam nípa bíbí ‘Īsā ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Ọ̀tọ̀ sì ni àsìkò tí àsọtẹ́lẹ̀ náà wá sí ìmúṣẹ.
Bákan náà, ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah an-Nisā’; 4:171 lórí àpólà ọ̀rọ̀-orúkọ yìí “ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ Rẹ̀”.


الصفحة التالية
Icon