Ẹ má ṣe bá ahlul-kitāb ṣàríyàn jiyàn àfi ní ọ̀nà t’ó dára jùlọ (èyí ni lílo al-Ƙur’ān àti hadīth. Ẹ má sì ṣe jà wọ́n lógun) àfi àwọn t’ó bá ṣàbòsí nínú wọn. Kí ẹ sì sọ pé: “A gbàgbọ́ nínú ohun tí Wọ́n sọ̀kalẹ̀ fún àwa àti ohun tí Wọ́n sọ̀kalẹ̀ fún ẹ̀yin. Ọlọ́hun wa àti Ọlọ́hun yín, (Allāhu) Ọ̀kan ṣoṣo ni. Àwa sì ni mùsùlùmí (olùjuwọ́-jusẹ̀-sílẹ̀) fún Un.”
____________________
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé alábòsí wulẹ̀ ni gbogbo àwọn ahlul-kitāb, àbòsí mìíràn ni Allāhu ń tọ́ka sí lára wọn nínú āyah yìí. Òhun sì ni bí àwọn ahlul-kitāb ṣe ń gbógun ti àwa mùsùlùmí àti bí wọ́n ṣe ń kọ̀ láti san ìsákọ́lẹ̀ fún ìjọba ’Islām.


الصفحة التالية
Icon