Òun ni Ẹni tí Ó ń bẹ̀rẹ̀ ẹ̀dá dídá. Lẹ́yìn náà, Ó máa dá a padà (sípò alààyè fún àjíǹde). Ó sì rọrùn jùlọ fún Un (láti ṣe bẹ́ẹ̀). TiRẹ̀ ni ìròyìn t’ó ga jùlọ nínú àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀. Òun sì ni Alágbára, Ọlọ́gbọ́n.
____________________
Ìròyìn t’ó ga jùlọ tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) fi ròyìn ara Rẹ̀ ni gbolóhùn “Kò sí ọlọ́hun tí ìjọ́sìn tọ́ sí àfi Allāhu.” Àti gbólóhùn yìí :“Kò sí kiní kan t’ó dà bí Rẹ̀…” (at-Tọbariy)