(Ẹ rántí) nígbà tí Allāhu sọ pé: “‘Īsā, dájúdájú Mo máa gbà ọ́ (kúrò lọ́wọ́ wọn).1 Mo máa gbé ọ wá sókè lọ́dọ̀ Mi. Mo sì máa fọ̀ ọ́ mọ́ lọ́dọ̀ àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́.2 Mo sì máa fi àwọn t’ó tẹ̀lé ọ borí àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́ títí di Ọjọ́ Àjíǹde. Lẹ́yìn náà, ọ̀dọ̀ Mi ni ibùpadàsí yín. Mo sì máa ṣe ìdájọ́ láààrin yín nípa ohun tí ẹ yapa ẹnu sí.
____________________
1 Wọ́n ṣẹ̀dá "mutawaffi" láti ara "wafāt/wafāh." Ìtúmọ̀ mẹ́ta ni wafāt/wafāh ní nínú al-Ƙur’ān, hadīth àti èdè Lárúbáwá. Àwọn ìtúmọ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: "maot" ikú, "naom" oorun àti "ƙọbd" gbígba n̄ǹkan tàbí gbígba ẹnì kan kúrò lọ́wọ́ ẹnì kan. Wafāt/wafāh túmọ̀ sí "maot" ikú nínú sūrah az-Zumọr; 39:42. Wafāt/wafāh túmọ̀ sí "naom" oorun nínú sūrah al-’Ani‘ām; 6:60. Wafāt/wafāh sì túmọ̀ sí "ƙọbd" gbígba ẹnì kan kúrò lọ́wọ́ ẹnì kan nínú sūrah āli ‘Imrọ̄n; 3:55 ati sūrah al-Mọ̄’dah; 5:117. Ìdí tí wafāt/wafāh ti ‘Īsā fi túmọ̀ sí gbígba ẹnì kan kúrò lọ́wọ́ ẹnì kan (ìyẹn, gbígbà tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) gba Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) kúrò lọ́wọ́ àwọn yẹhudi tí wọ́n pète pèrò láti kàn án mọ́ orí igi àgbélébùú, òhun ni pé, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ti sọ nípa ìṣẹ̀lẹ̀ náà pé, àwọn yẹhudi kò rí ‘Īsā ọmọ Mọryam pa, wọn kò sì rí i kàn mọ́ igi àgbélébùú, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà nínú sūrah an-Nisā’; 4:157-159.
Bákan náà, ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ hadīth Òjíṣẹ́ (sollalāhu 'alayhi wa sallam) t’ó ní àlàáfíà l’ó fi rinlẹ̀ pé ‘Īsā ọmọ Mọryam yóò padà sọ̀kalẹ̀ láti ojú sánmọ̀ ní òpin ayé láti wá ṣe àwọn iṣẹ́ ńlá ńlá kan. Kò sì níí sí rújúrújú kan kan nínú ìsọ̀kalẹ̀ ‘Īsā ọmọ Mọryam àti àwọn iṣẹ́ tí ó ń bọ̀ wá ṣe ní òpin ayé. Àmọ́ ìjọ Ahmadiyyah àti irú wọn mìíràn kò ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, wọ́n sì túmọ̀ wafāt/wafāh ti ‘Īsā ọmọ Mọryam sí ikú nítorí pé olùdásílẹ̀ ìjọ Ahmadiyyah ti sọra rẹ̀ di ‘Īsā ọmọ Mọryam. Àwọn ìjọ Ahmadiyyah sì ní ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀ digbí. Èyí sì tún jẹ́ ọ̀kan nínú ìdí pàtàkì tí ìjọ Ahmadiyyah fi yapa ’Islām. Wọ́n sì di kèfèrí. Ẹ kà á síwájú sí i nínú ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah an-Nisā’; 4:158.
2 Lára àṣìṣe àwọn kristiẹni ni bí wọ́n ṣe lérò pé àwọn gan-an ni al-Ƙur’ān ń tọ́ka sí pẹ̀lú gbólóhùn “àwọn t’ó tẹ̀lé ọ”, ìyẹn àwọn t’ó tẹ̀lé ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Ọ̀rọ̀ kò rí bẹ́ẹ̀ rárá. Ní àkọ́kọ́ náà, ẹlẹ́sìn ’Islām ni àwọn t’ó tẹ̀lé ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Àti ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) àti ọ̀wọ́ àwọn t’ó tẹ̀lé e lójú ayé rẹ̀, mùsùlùmí ni wọ́n gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe pera wọn bẹ́ẹ̀ nínú sūrah yìí, āyah 52. Ó tún wà bẹ́ẹ̀ nínú sūrah al-Mọ̄’dah; 5:111. Àmọ́ nípa àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́ lórí ọ̀rọ̀ ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām), ìsọ̀rí mẹ́ta ni wọ́n. Ìsọ̀rí kìíní ni ìjọ yẹhudi. Àwọn di kèfèrí nípasẹ̀ bí wọn kò ṣe gba ‘Īsā gbọ́ ní Òjíṣẹ́ àti bí wọ́n ṣe pète pèrò láti kàn án mọ́ igi àgbélébùú àti láti pa á, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) kó o yọ nínú ète wọn. Ìsọ̀rí yìí gan-an ló sì jẹyọ nínú sūrah yìí láààrin āyah 52 sí 56. (Síwájú sí i, àwọn t’ó tẹ̀lé ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām), tí wọ́n pera wọn ní mùsùlùmí àti àwọn yẹhudi t’ó ṣàì gbàgbọ́, tí wọ́n sì fẹ́ kan ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) mọ́gi àgbélébùú; àwọn igun méjèèjì náà l’ó tún jẹyọ nínú sūrah as-Sọff; 61:14.) Lórí àwọn ìjọ mẹ́ta t’ó di aláìgbàgbọ́ lórí ọ̀rọ̀ ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām), nasara ni ìjọ kejì. Wọ́n di kèfèrí nípasẹ̀ bí wọ́n ṣe sọ ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) di olúwa àti olùgbàlà lẹ́yìn Allāhu, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ‘Īsā ọmọ Mọryam kì í ṣe olúwa àti olùgbàlà fún ẹnì kan kan, kò sì pera rẹ̀ bẹ́ẹ̀ rí. Àwọn nasara wọ̀nyí ni Allāhu sọ nípa wọn nínú sūrah al-Mọ̄’idah; 5:17, 72 àti 73. Ìjọ kẹta ni ìjọ Ahmadiyyah. Wọ́n di kèfèrí nípasẹ̀ bí wọ́n ṣe gbàgbọ́ pé àwọn yẹhudi rí ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) kàn mọ́gi àgbélébùú, àmọ́ kò kú sórí rẹ̀. Ìgbàgbọ́ Ahmadiyyah yìí sì tako sūrah an-Nisā’; 4:157-159.


الصفحة التالية
Icon