(Rántí) nígbà tí ò ń sọ fún ẹni tí Allāhu ṣèdẹ̀ra fún, tí ìwọ náà ṣèdẹ̀ra fún1 pé: “Mú ìyàwó rẹ dání, kí o sì bẹ̀rù Allāhu.” O sì ń fi pamọ́ sínú ẹ̀mí rẹ ohun tí Allāhu yó ṣàfi hàn rẹ̀. Àti pé ò ń páyà àwọn ènìyàn. Allāhu l’Ó sì lẹ́tọ̀ọ́ jùlọ pé kí o páyà Rẹ̀. Nígbà tí Zaed ti parí bùkátà rẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ̀ (tí ó sì ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀), A ti ṣe é ní ìyàwó fún ọ nítorí kí ó má baà jẹ́ láìfí fún àwọn onígbàgbọ́ òdodo láti fẹ́ ìyàwó ọmọ-ọlọ́mọ tí wọ́n ń pè ní ọmọ wọn nígbà tí wọ́n bá ti parí bùkátà wọn lọ́dọ̀ wọn (tí wọ́n sì ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀). Àṣẹ Allāhu sì gbọ́dọ̀ ṣẹ.2
____________________
1. Ẹni yìí ni Zaed ọmọ Hārithah (rọdiyallāhu 'anhu). Ìdẹ̀ra Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) lórí rẹ̀ ni pé, Allāhu ṣe é ní mùsùlùmí. Ìdẹ̀ra Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) lórí rẹ̀ ni pé, Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) mú un kúrò lóko ẹrú. Ó sọ ọ́ di olómìnira. 2. Ohun tí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) fi pamọ́ sínú ẹ̀mí rẹ̀ ni gbólóhùn yìí: "Nígbà tí Zaed ti parí bùkátà rẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ̀ (tí ó sì ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀), A ti ṣe é ní ìyàwó fún ọ …". Àmọ́ kàkà kí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kéde gbólóhùn yìí fún àwọn mùsùlùmí, kí ó sì jíṣẹ́ fún Zaed, ńṣe ni Ànábì ń sọ fún un pé: "Mú ìyàwó rẹ dání..." Ohun tí ó sì fa èyí fún Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ni pé, kí àwọn ṣọ̀bẹ-ṣèlu mùsùlùmí àti àwọn aláìgbàgbọ́ má baà wí pé: "Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) l’ó fi Zaenab fún Zaed, ọmọ rẹ̀. Ó tún fi ìyàwó tí ọmọ rẹ̀ kọ̀ sílẹ̀ ṣaya…". Zaed kì í sì ṣe ọmọ Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Hārithah ni bàbá t’ó bí Zaed lọ́mọ. Ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ni ìdí tí àwọn aṣíwájú rere (r.ahm) fi sọ pé, nínú gbogbo āyah al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé kò sí èyí tí ó lágbára lára Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) láti fi jíṣẹ́ fún àwọn ènìyàn t’ó tó āyah: "Nígbà tí Zaed ti parí bùkátà rẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ̀ (tí ó sì ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀), A ti ṣe é ní ìyàwó fún ọ …". Nítorí náà, ẹ jìnnà sí àwọn ìtànkítàn tí àwọn kristiẹni bá ń sọ kiri nípa ìṣẹ̀lẹ̀ náà, kò sí èyí tí ó fẹsẹ̀ rinlẹ̀ nínú rẹ̀ àfi èyí tí A sọ sókè yìí. Kíyè sí i, bóyá ni Ànábì tàbí Òjíṣẹ́ kan nínú àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu (a.s.w.) wà tí àwọn ọ̀tá ẹ̀sìn ’Islām kì í sọ ìsọkúsọ nípa rẹ̀. Ìṣe àti àṣà wọn nìyẹn. Ẹni tí a sì lérò pé àwọn kristiẹni máa pọ́nlé, ohun tí wọ́n tún sọ nípa rẹ̀ ju fífi ẹ̀sùn ìyàwó púpọ̀ kan Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam) àti fífẹ́ tí ó fẹ́ Zaenab tí Zaed kọ̀ sílẹ̀. Pípè tí àwọn kristiẹni ń pe Ànábì ‘Īsā ni ọmọ Allāhu, pípè tí wọ́n ń pè é ní ọlọ́hun ọmọ, pípè tí wọ́n ń pè é ní olúwa àti olùgbàlà, ó burú yéye ju fífi ẹ̀sùn ìyàwó púpọ̀ kan Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam), gẹ́gẹ́ bí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ti ṣe pe àkíyèsí wa sí aburú rẹ̀ nínú sūrah Mọryam; 19:88-95. Àmọ́ àwọn kristiẹni kò fura!


الصفحة التالية
Icon