Dájúdájú Allāhu àti àwọn mọlāika Rẹ̀ ń kẹ́ Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Ẹ̀yin tí ẹ gbàgbọ́ ní òdodo, ẹ tọrọ ìkẹ́ fún un, kí ẹ sì kí i ní kíkí àlàáfíà.
____________________
Níkété tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sọ āyah yìí kalẹ̀ ni àwọn Sọhābah (r.ahm) bèèrè ohun tí àwọn náà yóò fi máa tọrọ ìkẹ́ fún Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sì kọ́ wọn ní sọlātu ’Ibrọ̄hīmiyyah. Ẹ̀gbàwá kan nìyí:
اللَّهُمَّ صَلِّ عَلَى مُحَمَّدٍ وَعَلَى آلِ مُحَمَّدٍ كَمَا صَلَّيْتَ عَلَى آلِ إِبْرَاهِيمَ إِنَّكَ حَمِيدٌ مَجِيدٌ اللَّهُمَّ بَارِكْ عَلَى مُحَمَّدٍ وَعَلَى آلِ مُحَمَّدٍ كَمَا بَارَكْتَ عَلَى آلِ إِبْرَاهِيمَ إِنَّكَ حَمِيدٌ مَجِيدٌ.
Allahummọ sọlli ‘alā Muhammadin wa ‘alā āli Muhammadin kamọ̄ sọllaeta ‘alā āli ’Ibrọ̄hīmọ ’innaka Hamīdun Mọjīd. Allahummọ bārik ‘alā Muhammadin wa ‘alā āli Muhammadin kamọ̄ bārọkta ‘alā āli ’Ibrọ̄hīmọ ’innaka Hamīdun Mọjīd. (Bukọ̄riy àti Muslim)
Gbólóhùn wọ̀nyí tún tọ súnà; “sọlla-llāhu ‘aleehi wa sallam” tàbí “‘aleehi sọlātun wa salām.” Kíyè sí i, kò sí aburú níbi kí mùsùlùmí máa sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ kí ó sì fi gbólóhùn kan ní ọ̀dọ̀ ara rẹ̀ tọrọ ìkẹ́ àti ọlà fún Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò tí ì dáràn nítorí pé, àwọn Sọhābah náa (r.ahm) máa ń ṣe bẹ́ẹ̀. Ẹ̀yin náà ẹ wo bí àwọn àáfà sunnah ṣe ń ṣe asọlātu fún Ànábì nínú àwọn ọ̀rọ̀ ìṣaájú nínú àwọn tírà wọn. Kò sí aburú nínú èyí rárá. Ṣùgbọ́n mùsùlùmí yóò ṣe àgbékalẹ̀ ìhun asọlātu dáràn tí ó bá fi lè kó sínú ọ̀kan nínú àwọn n̄ǹkan mẹ́fà kan. Ìkíní: Lílo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó lòdì sí òfin àti àdìsọ́kàn ’Islām nínú àwọn gbólóhùn asọlātu náà. Ìkejì: Sísọ gbólóhùn asọlātu yẹn gan-angan di ìlànà tí wọn yóò máa pèpè sí, tí irúfẹ́ gbólóhùn náà yóò fi wá dà bí ẹni pé hadīth kan l’ó gbà á wá, tí kò sì rí bẹ́ẹ̀. Ìkẹta: Ṣíṣe àgbékalẹ̀ òǹkà kan tàbí àsìkò kan tàbí ọjọ́ kan ní pàtó fún ṣíṣe irúfẹ́ asọlātu àdáhun náà. Ìkẹrin: Ṣíṣe àgbékalẹ̀ ìlànà kan ní pàtó fún ṣíṣe irúfẹ́ asọlātu àdáhun náà, bí kí wọ́n wí pé ẹnì kan kò gbọdọ̀ kà á àfi pẹ̀lú àlùwàlá. Ìkarùn-ún: Ṣíṣe àgbékalẹ̀ láádá fún irúfẹ́ asọlātu àdáhun náà, tí èyí yó sì bí níní àdìsọ́kàn nípa àwọn láádá àgbélẹ̀rọ náà. Ìkẹfà: Kíka irúfẹ́ asọlātu àdáhun náà kún ìmísí mímọ́ láti ọ̀dọ̀ Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) tàbí ṣíṣe àfitì irúfẹ́ asọlātu àdáhun náà sí ọ̀dọ̀ Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ní ti irọ́. Àwọn n̄ǹkan mẹ́fẹ̀ẹ̀fà wọ̀nyí l’ó ṣe àkóbá ńlá fún àwọn asọlātu àdáhun kan bíi sọlātul-fātih, sọlātu tunjīnā, sọlātul-gaebiyyah, sọlātu rọf‘il-’a‘mọ̄l, sọlātul-kamsah, jaoharatul-kamọ̄l, dalā’ilul-kaerāt, sọlawātul-kibrītu al-’ahmọr àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Àwọn onisūfi ni wọ́n ṣe àdádáálẹ̀ àwọn asọlātu aburú wọ̀nyẹn sínú ẹ̀sìn. Ìṣìnà àti òfò pọ́nńbélé sì ni gbogbo wọn.


الصفحة التالية
Icon