Òun ni Ẹni tí Ó dá ohunkóhun t’ó wà lórí ilẹ̀ fun yín pátápátá. Lẹ́yìn náà, Ó wà l’ókè sánmọ̀, Ó sì ṣe wọ́n tógún régé sí sánmọ̀ méje. Òun sì ni Onímọ̀ nípa gbogbo n̄ǹkan.
____________________
Àwọn kristiẹni wí pé, “Sūrah al-Baƙọrah; 2:29 tako sūrah an-Nāzi‘āt; 79:27-30 nítorí pé, ìkíní ń sọ pé ilẹ̀ ni Allāhu kọ́kọ́ dá ṣíwájú sánmọ̀, ìkejì sì ń sọ pé sánmọ̀ ni Allāhu kọ́kọ́ dá ṣíwájú ilẹ̀!”
Èsì: Èyí jẹ́ “ìtakora tófẹ́jọbẹ́ẹ̀”, kì í ṣe “ìtakora tóríbẹ́ẹ̀”. Àlàyé rẹ̀ nìyí, ìṣẹ̀dá ilẹ̀ ṣíwájú ìṣẹ̀dá sánmọ̀ gẹ́gẹ́ bí āyah inú sūrah Baƙọrah yẹn ṣe fi rinlẹ̀. Àmọ́ kì í ṣe ọ̀rọ̀ nípa ìṣẹ̀dá ilẹ̀ ni āyah sūrah an-Nāzi‘āt ń sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) kò sì lo ọ̀rọ̀ t’ó túmọ̀ sí ìṣẹ̀dá ilẹ̀ nínú āyah t’Ó ti dárúkọ ilẹ̀, ìyẹn āyah 30 nínú sūrah
an-Nāzi‘āt. Kalmọh “dahāhā” ni Allāhu lò níbẹ̀ fún ilẹ̀. Ìtúmọ̀ “dahāhā” sì ni pé “Ó tẹ́ ilẹ̀ pẹrẹsẹ”. Ẹ tún wo sūrah al-Hijr; 15:19. Àlàyé tí àwọn onímọ̀ ’Islām mú wá nípa èyí ni pé, ìṣẹ̀dá ilẹ̀ wáyé fún ọjọ́ méjì. Lẹ́yìn náà, ìṣẹ̀dá gbogbo ohun t’ó máa wà nínú ilẹ̀ ní àwọn igi, àwọn ibúdò, àwọn àpáta, àwọn àlùmọ́nì ilẹ̀, àwọn oúnjẹ ènìyàn, àwọn oúnjẹ àlùjànnú àti àwọn oúnjẹ gbogbo abẹ̀mí wáyé fún ọjọ́ méjì. Lẹ́yìn náà, ìṣẹ̀dá sánmọ̀ pẹ̀lú àwọn ẹrù inú rẹ̀ ní àwọn ìràwọ̀, òṣùpá, òòrùn àti òjò wáyé fún ọjọ́ méjì. Àpapọ̀ gbogbo ọjọ́ ìṣẹ̀dá wọ̀nyí jẹ́ ọjọ́ mẹ́fà. Àmọ́, ilẹ̀ tòhun ti àwọn ẹrù inú rẹ̀ sì wà roboto títí Allāhu fi parí ìṣẹ̀dá sánmọ̀. Sísọ ilẹ̀ roboto di ilẹ̀ pẹrẹsẹ wá ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìṣẹ̀dá sánmọ̀. Ohun tí ó sì fa èyí ni pé, ilẹ̀ bùkátà sí ìmọ́lẹ̀ òṣùpá àti ìmọ́lẹ̀ òòrùn nítorí kí àwọn ohun gbogbo tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ti ṣẹ̀dá sínú ilẹ̀ lè máa gbèrú sí i. Báyìí ni Allāhu ṣe tẹ́ ilẹ̀ pẹrẹsẹ fún òṣùpá, ìràwọ̀ àti òòrùn nítorí kí wọ́n lè rí iṣẹ́ ṣe lára ilẹ̀, Ó sì fi àwọn àpáta inú ilẹ̀ ṣe èṣó t’Ó fi kan ilẹ̀ nítorí kí àwọn ibúdò má lè yí ilẹ̀ dànù. Nítorí náà, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ti parí ìṣẹ̀dá ilẹ̀ àti ohun inú rẹ̀ ṣíwájú ìṣẹ̀dá sánmọ̀. Àmọ́ Ó sọ ilẹ̀ roboto di ilẹ̀ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìṣẹ̀dá sánmọ̀. Kì í ṣe pé Ó ṣẹ̀dá ilẹ̀ lẹ́yìn sánmọ̀. Àkàwé ìṣẹ̀lẹ̀ yìí dà bíi kíkọ́ ilé àti ṣíṣí ilé. Kò sí oníṣirò tí ó máa ṣí ọjọ́ ìkọ́lé mọ́ ọjọ́ ìṣílé àfi ẹni tí kò bá yanjú nínú ẹ̀kọ́ ìṣírò. Nítorí náà, kò sí ìtakora tóríbẹ́ẹ̀ nínú àwọn āyah náà. W-Allāhu ’a‘lam.


الصفحة التالية
Icon