Igun kan nínú àwọn ahlul-kitāb wí pé: “Ẹ lọ gbàgbọ́ nínú ohun tí Wọ́n sọ̀kalẹ̀ fún àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo níbẹ̀rẹ̀ ọjọ́, kí ẹ sì takò ó níparí rẹ̀, bóyá àwọn mùsùlùmí (kan) máa ṣẹ́rí padà (sẹ́yìn nínú ẹ̀sìn ’Islām).
____________________
Èyí jẹ́ ète kan nínú àwọn ète tí àwọn ahlul-kitāb ń lò. Ète náà ni pé, àwọn kan nínú wọn máa kó sínú ẹ̀sìn ’Islām ní àsìkò kan. Wọn kò sì níí ’Islām í ṣe nítorí pé àìgbàgbọ́ kò yé bá wọn fínra nínú ọkàn wọn, gẹ́gẹ́ bí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe fìdí èyí rinlẹ̀ bẹ́ẹ̀ nínú sūrah al-Mọ̄’idah; 5:61. Àmọ́ tòhun ti bẹ́ẹ̀ náà wọ́n kó sínú ’Islām ní àsìkò náà nítorí kí wọ́n lè padà kéde pé àwọn kò ṣe ’Islām mọ́. Irú àwọn wọ̀nyí ni wọ́n sọra wọn di "akéúgbajésù". Ìjàǹbá kan nínú àwọn ìjàǹbá tí ahlul-kitāb ń ṣe fún àwa Mùsùlùmí ni èyí. Wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀ láti fi ṣẹ́rí àwọn tí ìgbàgbọ́ òdodo wọn nínú Allāhu kò tí ì rinlẹ̀ àti àwọn t’ó ṣẹ̀ṣẹ̀ fẹ́ gba ẹ̀sìn ’Islām. Kí irú àwọn wọ̀nyí lè máa wí pé: "Tí kò bá jẹ́ pé irọ́ wà nínú ’Islām ni, lágbájá àti tàmẹ̀dò kò níí di akéúgbajésù." Kò sì sí lágbájá àti tàmẹ̀dò kan t’ó sọra wọn di akéúgbajésù bí kò ṣe àwọn oníjàǹbá. Àti pé, èdè ni kéú, ìmọ̀ ẹ̀sìn ni al-Ƙur’ān àti hadīth. Àwọn oníjàǹbá wọ̀nyí kì í sì ṣe onímọ̀ ẹ̀sìn. Ìdí nìyí tí ẹ̀yin kò fi lè rí akéúgbajésù kan tí ó lè ko mùsùlùmí onímọ̀ ẹ̀sìn lójú. Nítorí náà, ẹ má ṣe gbẹ̀tàn. ’Islām nìkan ṣoṣo ni òdodo. Ìṣìnà pọ́nńbélé ni gbogbo ẹ̀sìn yòókù pátápátá.


الصفحة التالية
Icon