Dájúdájú Àwa fi òdodo rán ọ níṣẹ́. (O sì jẹ́) oníròó-ìdùnnú àti olùkìlọ̀. Kò sí ìjọ kan (ṣíwájú rẹ) àfi kí olùkìlọ̀ ti rè kọjá láààrin wọn.
____________________
Āyah yìí jẹ́ ọ̀kan nínú ọ̀nà tí ìjọ Ahmadiyyah gbà di kèfèrí. Ìdí ni pé, nítorí āyah yìí ni ìjọ náà fi pe gbogbo òrìṣà ní ànábì tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) rán níṣẹ́ sí ayé. Ìtọ́kasí wọn nìyí: “In pursuance of this doctrine, he (mirza Ghulam Ahmad al-Ƙadiyyaanii) testified to the truth of Krishna, Ram Chandra and Buddha, the prophets of India, and Zoroaster, the prophet of Persia, and described the rejection of their claims as, in a sense, amounting to a denial of the universal Providence of God.” Ìtúmọ̀ “Láti lè tẹ̀lé ìgbàgbọ́ yìí l’ó mú kí mirza Ghulam Ahmad jẹ́rìí pé òdodo ni òrìṣà Krishna, òrìṣà Ram Chandra àti òrìṣà Buda, tí wọ́n jẹ́ àwọn ànábì ilẹ̀ India. Àti òrìṣà Zoroaster, tí ó jẹ́ ànábì ilẹ̀ Persia. Mirza Ghulam Ahmad sì gbà pé ẹni tí ó bá tako àwọn òrìṣà náà, ó ti tako oore tí Allāhu ṣe fún àgbáyé.” Ahmadiyyah Movement, láti ọwọ́ Bashirud-din Mahmud Ahmad, ojú ewé: 69. Bákàn náà, ìjọ Ahmadiyyah tún gbàgbọ́ lábẹ́ āyah yìí pé kò sí ìlú tí Allāhu kò ti gbé Òjíṣẹ́ kan dìde. Èyí kì í ṣe àgbọ́yé āyah yìí. Àti pé ìgbàgbọ́ wọn yìí tako sūrah al-Furƙọ̄n; 25:51. Lẹ́yìn náà, ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Ƙọsọs; 28:46.


الصفحة التالية
Icon