A sì sọ pé: “Ādam, ìwọ àti ìyàwó rẹ, ẹ máa gbé nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra. Kí ẹ máa jẹ nínú rẹ̀ ní gbẹdẹmukẹ ní ibikíbi tí ẹ bá fẹ́. Kí ẹ sì má ṣe súnmọ́ igi yìí, kí ẹ má baà wà nínú àwọn alábòsí.”
____________________
Nípa èso tí Ànábì Ādam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) jẹ, ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-’Arọ̄f; 7:22.


الصفحة التالية
Icon