Bèèrè wò lọ́wọ́ àwọn tí A rán níṣẹ́ ṣíwájú rẹ nínú àwọn Òjíṣẹ́ Wa (pé): "Ǹjẹ́ A sọ àwọn kan di ọlọ́hun tí wọn yóò máa jọ́sìn fún lẹ́yìn Àjọkẹ́-ayé bí?"
____________________
“Bèèrè wò lọ́wọ́ àwọn tí A rán níṣẹ́ ṣíwájú rẹ nínú àwọn Òjíṣẹ́ Wa”. Àgbọ́yé méjì ni àwọn tafsīr mú wá lórí rẹ̀. Àgbọ́yé kìíní ni pé, ìbéèrè náà wáyé nínú ìrìn-àjò òru àti ìgun-sánmọ̀ tí Allāhu mú Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam) rìn. Àgbọ́yé kejì ni pé, ìbéèrè náà wáyé láààrin Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) àti àwọn t’ó nímọ̀ nípa Taorāt àti ’Injīl. Ìyẹn ni pé, kí ni àwọn tírà méjèèjì sọ nípa “ta ni ìjọ́sìn tọ́ sí, ṣé Allāhu ni tàbí àwọn ọlọ́hun mìíràn?” Dídárúkọ àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu ní àyè yìí dípò àwọn tírà wọn jọ bí Allāhu ṣe pàṣẹ pé “Tí ẹ bá yapa ẹnu nípa kiní kan, ẹ ṣẹ́rí rẹ̀ sí ọ̀dọ̀ Allāhu àti ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ (sollalāhu 'alayhi wa sallam),…” (ìyẹn nínú sūrah an-Nisā’; 4:59), tí èyí sì túmọ̀ sí al-Ƙur’ān àti sunnah Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam).


الصفحة التالية
Icon