Kí ni òun bí kò ṣe ẹrúsìn kan tí A ṣe ìdẹ̀ra fún. A sì ṣe é ní àpẹẹrẹ rere fún àwọn ọmọ ’Isrọ̄’īl.
____________________
Nígbà tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) fi iná wíwọ̀ rínlẹ̀ fún àwọn òrìṣà àti àwọn abọ̀rìṣà wọn, ìyẹn nínú sūrah al-’Ambiyā’; 21:98-100, àwọn abọ̀rìṣà náà bá mú ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) wá gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ òrìṣà àkúnlẹ̀bọ t’ó máa wọná. Allāhu (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sì ṣàfọ̀mọ́ ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) fúnra Rẹ̀ pé kò sọra rẹ̀ d’òòṣà, àmọ́ àwọn tí wọ́n sọ ọ́ d’òòṣà ló máa wọná. Nítorí náà, ọ̀rọ̀ ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) kò jọ ọ̀rọ̀ àwọn t’ó sọra wọn d’òòṣà lẹ́yìn Allāhu (subhānahu wa ta'ālā). Irú āyah yìí tún ni āyah tí Allāhu (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ti pé àwọn òrìṣà àkúnlẹ̀bọ ní òkú, ìyẹn nínú sūrah an-Nahl; 16:21. Èyí tún ni ìjọ Ahmadiyyah àti ìjọ asòòkùn sẹ́sìn mìíràn tún sọ pé òkú ni ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Ọ̀rọ̀ kò sì rí bẹ́ẹ̀ rárá nítorí pé bí ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) bá ti kú ni Òjíṣẹ́ Allāhu (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kò níí sọ pé ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ń padà bọ̀ lópin aye, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe rinlẹ̀ bẹ́ẹ̀ nínú àwọn hadith rẹ̀ t’ó fẹsẹ̀ rinlẹ̀. Àmọ́ sá, ìdí tí ìjọ Ahmadiyyah fi gbà pé ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ti kú ni pé, olùdásílẹ́ ìjọ wọn, mirza ghulam Ahmad ti sọ’ra rẹ di ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) mọ́ wọn lọ́wọ́. Ìdí sì nìyí tí ìjọ Ahmadiyyah fi ń pè é ní “Mọsīh táàńretí”. Òpùrọ̀ pọ́nńbelé sì ni ọ̀gbẹni náà.


الصفحة التالية
Icon