Dájúdájú àwọn t’ó ń ṣàdéhùn fún ọ (pé àwọn kò níí fẹsẹ̀ fẹ́ẹ lójú ogun), dájúdájú Allāhu ni wọ́n ń ṣàdéhùn fún. Ọwọ́ Allāhu wà lókè ọwọ́ wọn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá tú àdéhùn rẹ̀, ó tú u fún ẹ̀mí ara rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì mú àdéhùn t’ó ṣe fún Allāhu ṣẹ, (Allāhu) yóò fún un ní ẹ̀san ńlá.
____________________
Èyí fi rinlẹ̀ pé, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ní ọwọ́ ní ti pàápàá àti ní ti bí ó ṣe bá títóbi Rẹ̀ mu. Àmọ́ àgbọ́yé āyah yìí jọ ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:15.


الصفحة التالية
Icon