Kí ẹ sì mọ̀ pé dájúdájú Òjíṣẹ́ Allāhu wà lààrin yín. Tí ó bá jẹ́ pé ó ń tẹ̀lé yín níbi ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ nínú ọ̀rọ̀ (t’ó ń ṣẹlẹ̀) ni, dájúdájú ẹ̀yin ìbá ti kó o sínú ìdààmú. Ṣùgbọ́n Allāhu jẹ́ kí ẹ nífẹ̀ẹ́ sí ìgbàgbọ́ òdodo. Ó ṣe é ní ọ̀ṣọ́ sínú ọkàn yín. Ó sì jẹ́ kí ẹ kórira àìgbàgbọ́, ìwà burúkú àti ìyapa àṣẹ. Àwọn wọ̀nyẹn ni àwọn olùmọ̀nà.
____________________
Nítorí gbólóhùn yìí “Kí ẹ sì mọ̀ pé dájúdájú Òjíṣẹ́ Allāhu wà lààrin yín”, àwọn onibidiah bí ìjọ Tijaniyyah àti ìjọ Ahmadiyyah lérò pé a sì lè rí Ànábì wa Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) lẹ́yìn ikú rẹ̀ lójú ayé. Kò rí bẹ́ẹ̀ rárá. Àmọ́ gbólóhùn náà dúró sórí “láààrin àsìkò ìṣẹ̀mí Ànábì wa Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) láààrin àwọn Sọhābah rẹ̀”. Irú gbólóhùn t’ó tún lọ bẹ́ẹ̀ ni èyí t’ó wà nínú sūrah al-Mujādilah; 58:12.


الصفحة التالية
Icon