Tí ẹ bá páyà pé ẹ ò níí ṣe déédé nípa (fífẹ́) ọmọ òrukàn, ẹ fẹ́ ẹni t’ó lẹ́tọ̀ọ́ si yín nínú àwọn obìnrin; méjì tàbí mẹ́ta tàbí mẹ́rin. Ṣùgbọ́n tí ẹ bá páyà pé ẹ ò níí ṣe déédé, (ẹ fẹ́) ẹyọ kan tàbí ẹrúbìnrin yín. Ìyẹn súnmọ́ jùlọ pé ẹ ò níí ṣàbòsí.
____________________
Kíyè sí i, àgbọ́yé “méjì” ni pé “fẹ́ méjì”, àgbọ́yé “mẹ́ta” ni pé “fẹ́ mẹ́ta”, àgbọ́yé “mẹ́rin” sì ni pé, “fẹ́ mẹ́rin”. Àgbọ́yé ọ̀rọ̀ àsọpọ̀ “wa” t’ó sì jẹyọ láààrin “mọthnā wa thulātha wa rubā‘” ni “tàbí”. Ìyẹn ni pé, “fẹ́ méjì tàbí mẹ́ta tàbí mẹ́rin”. Níwọ̀n ìgbà tí o ò bá gbọ́ “méjì” yé sí “fẹ́ méjì papọ̀ ní ọjọ́ kan náà”, tí o ò gbọ́ “mẹ́ta” yé sí “fẹ́ mẹ́ta papọ̀ ní ọjọ́ kan náà”, tí o ò sí gbọ́ “mẹ́rin” yé sí “fẹ́ mẹ́rin papọ̀ ní ọjọ́ kan náà”, o ò gbọ́dọ̀ gbọ́ “mọthnā wa thulātha wa rubā‘” yé sí “fẹ́ mẹ́sàn-án” ìyẹn, nípasẹ̀ lílo ọ̀rọ̀-àsopọ̀ “àti” fún ṣíṣírò méjì, mẹ́ta àti mẹ́rin papọ̀ mọ́ra wọn. Má sì ṣe sọ̀rọ̀ ní ìsọ̀rọ̀ àwọn aláìmọ̀kan nípa sísọ pé, “mẹ́ ni Ọlọ́hun wí”. Wọ́n ń parọ́ mọ́ Allāhu ni. Allāhu kò sọ “mẹ́”. Àwọn ni ìyà “mẹ́” ń wù ú jẹ. Bákan náà, má ṣe korò ojú sí fífẹ́ ìyàwó dé orí méjì tàbí mẹ́ta tàbí mẹ́rin. Ìyẹn kì í ṣe dandan. Àti pé, mẹ́rin yẹ ọkùnrin ju ṣíṣe zinā pẹ̀lú “mẹ́” lọ. Kò sì dìgbà tí ọkọ bá tó ṣe mọthnā kí ó tó lè jẹ̀bi ẹ̀sùn àìṣe déédé lọ́dọ̀ àwọn ìyàwó rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni! Ọkọ lè jẹ̀bi ẹ̀sùn àìṣe déédé, kódà kó jẹ́ oníyàwó kan péré, níwọ̀n ìgbà tí ó bá ti jẹ́ ahun, aláìbìkátà tàbí alápámáṣiṣẹ́ ọkùnrin. Wòóore! Pẹ̀lú āyah yìí, mẹ́rin lòpin òǹkà àpapọ̀ ìyàwó t’ó lè wà nípò ìyàwó fún mùsùlùmí ẹyọ kan. Òfin t’ó rọ̀ mọ́ òǹkà àpapọ̀ ìyàwó Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) yàtọ̀ sí èyí. Āyah tiwa ni èyí, sūrah al-’Ahazāb; 33:50-52 ni ti Ànábì wa Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Kò dojú rú rárá. Al-hamdu lillāh.


الصفحة التالية
Icon