Àwọn t’ó ń ṣe sìná nínú àwọn obìnrin yín, ẹ wá ẹlẹ́rìí mẹ́rin nínú yín tí ó máa jẹ́rìí lé wọn lórí. Tí wọ́n bá jẹ́rìí lé wọn lórí, kí ẹ dè wọ́n mọ́ inú ilé títí ikú yóò fi pa wọ́n tàbí (títí) Allāhu yóò fi fún wọn ní ọ̀nà (mìíràn).
____________________
Èyí ni òfin àkọ́kọ́ lórí ìdíyàjẹ onísìná obìnrin. Lẹ́yìn náà, òfin lílẹ onísìná lókò pa dé lórí ẹni tí ó bá ṣe sìná lẹ́yìn tí ó ti ṣe nikāh rí. Èyí sì ni ọ̀nà mìíràn tí Allāhu fún wọn láti fi bá abilékọ t’ó ṣe sìná wí. Òfin àkọ́kọ́ yẹn ni àwọn kògbédè-ó-gbékèé ń lò fún ẹ̀há (hijāb) àwọn obìnrin mùsùlùmí, tí ó sì jẹ́ pé ọ̀tọ̀ ni āyah ìdíyàjẹ onísìná bí tinú sūrah an-Nūr; 24:2, ọ̀tọ̀ sì ni āyah ẹ̀há (hijāb) bí tinú sūrah an-Nūr; 24:31 àti sūrah al-’Ahzāb; 33:59.


الصفحة التالية
Icon