Ẹ̀yin tí ẹ gbàgbọ́ ní òdodo, ẹ tẹ̀lé (àṣẹ) Allāhu, ẹ tẹ̀lé (àṣẹ) Òjíṣẹ́ náà àti àwọn aláṣẹ nínú yín. Nítorí náà, tí ẹ bá yapa ẹnu sí kiní kan, ẹ ṣẹ́rí rẹ̀ sí ọ̀dọ̀ Allāhu àti Òjíṣẹ́ (sollalāhu 'alayhi wa sallam), tí ẹ bá gbàgbọ́ nínú Allāhu àti Ọjọ́ Ìkẹ́yìn. Ìyẹn lóore jùlọ, ó sì dára jùlọ fún ìkángun ọ̀rọ̀.
____________________
Kíyè sí i, ṣíṣẹ́rí ìyapa-ẹnu padà sí ọ̀dọ̀ Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) àti ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ Rẹ̀ (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kò túmọ̀ sí gbígbé ìyapa-ẹnu lọ pàdé Allāhu l’ọ́jọ́ Àjíǹde tàbí gbígbé ìyapa-ẹnu lọ síbi sàréè Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) bí kò ṣe pé fífi al-Ƙur’ān àti sunnah Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) t’ó fẹsẹ̀ rinlẹ̀ yanjú àwọn ìyapa-ẹnu pátápátá. Gbólóhùn yìí jọ sūrah aṣ-Ṣūrọ̄; 42:10. Ìyẹn nígbà tí Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) wà nílé ayé ṣíwájú kí ó tó kú. Àmọ́ lẹ́yìn ikú rẹ̀ (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kò sí àǹfààní fún ẹnikẹ́ni mọ́ láti lọ bá a nídìí sàréè rẹ̀ fún lílo àṣẹ yẹn. Tí ènìyàn kan bá dán an wò pẹ́rẹ́, ó máa kó sínú ẹbọ ńlá. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah āli-’Imrọ̄n; 3:101.


الصفحة التالية
Icon