A ò rán Òjíṣẹ́ kan níṣẹ́ àfi nítorí kí wọ́n lè tẹ̀lé e pẹ̀lú ìyọ̀ǹda Allāhu. Tí ó bá jẹ́ pé nígbà tí wọ́n ṣàbòsí sí ẹ̀mí ara wọn, wọ́n wá bá ọ, wọ́n sì tọrọ àforíjìn Allāhu, tí Òjíṣẹ́ sì tún bá wọn tọrọ àforíjìn, wọn ìbá kúkú rí Allāhu ní Olùgba-ìronúpìwàdà, Àṣàkẹ́-ọ̀run.
____________________
Ìyẹn nígbà tí Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) wà nílé ayé ṣíwájú kí ó tó kú. Àmọ́ lẹ́yìn ikú rẹ̀ (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kò sí àǹfààní fún ẹnikẹ́ni mọ́ láti lọ bá a nídìí sàréè rẹ̀ fún lílo àṣẹ yẹn. Tí ènìyàn kan bá dán an wò pẹ́rẹ́, ó máa kó sínú ẹbọ ńlá. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah āli-’Imrọ̄n; 3:101.


الصفحة التالية
Icon