Kí l’ó ṣe yín tí ẹ ò níí jagun fún ẹ̀sìn Allāhu, nígbà tí àwọn aláìlágbára nínú àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé (sì ń bẹ lórí ilẹ̀), àwọn t’ó ń sọ pé: “Olúwa wa, mú wa jáde kúrò nínú ìlú yìí, ìlú àwọn alábòsí. Fún wa ní aláàbò kan láti ọ̀dọ̀ Rẹ́. Kí Ó sì fún wa ní alárànṣe kan láti ọ̀dọ̀ Rẹ.”
____________________
Āyah yìí ń jẹ́ kí á mọ̀ pé, yàtọ̀ sí pé ogun ẹ̀sìn wà fún ààbò ẹ̀sìn wa, kí ó fi lè wà ní òmìnira, ó tún wà fún ìgbàlà àwọn onígbàgbọ́ òdodo lọ́kùnrin, lóbìnrin àti lọ́mọdé tí wọ́n wà lábẹ́ ìmúnisìn ìjọba kèfèrí. Lóde òní yìí, ìbá jẹ́ pé a rí ikọ̀ ogun ’Islām t’ó dúró déédé lórí sunnah Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam), àwọn mùsùlùmí aláìlágbára ìbá ti kúrò nínú ìnira tí ìjọba kèfèrí ń fi kàn wọ́n lójoojúmọ́. Allāhu, ṣàrànṣe Rẹ fún wa lórí àwọn ọ̀tá ẹ̀sìn Rẹ àti ọ̀tá àwọn ẹrúsìn Rẹ.


الصفحة التالية
Icon