Wọ́n ṣe àwọn n̄ǹkan dáadáa ní ẹ̀tọ́ fun yín lónìí. Àti oúnjẹ àwọn tí A fún ní tírà, ẹ̀tọ́ ni fun yín.1 Oúnjẹ tiyín náà, ẹ̀tọ́ ni fún wọn. (Ẹ̀tọ́ ni fun yín láti fẹ́) àwọn olómìnira nínú àwọn onígbàgbọ́ òdodo lóbìnrin àti àwọn olómìnira lóbìnrin nínú àwọn tí A fún ní tírà ṣíwájú yín, nígbà tí ẹ bá ti fún wọn ní ṣọ̀daàkí wọn; ẹ fẹ́ wọn ní fífẹ́ (bí ’Islām ṣe ní kí ẹ fẹ́ ìyàwó), láì níí bá wọn ṣe sìná (ṣíwájú yìgì) láì sì níí yàn wọ́n lálè.2 Ẹnikẹ́ni tí ó bá lòdì sí ìgbàgbọ́ òdodo, iṣẹ́ rẹ̀ ti bàjẹ́. Ní Ọjọ́ Ìkẹ́yìn, ó sì máa wà nínú àwọn ẹni òfò.
____________________
1 Kíyè sí i, àwọn kan lérò pé gbólóhùn yìí “Àti oúnjẹ àwọn tí A fún ní tírà, ẹ̀tọ́ ni fun yín.” kó oúnjẹ ọdún àwọn kristiẹni sínú. Rárá o. Ànábì wa Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sọ al-Ƙur’ān kalẹ̀ fún, kò jẹ oúnjẹ ọdún mìíràn yàtọ̀ sí oúnjẹ ọdún ’Islām. Bákan náà, àwọn Sọhābah (r.ahm.), kò sí ẹni t’ó jẹ oúnjẹ ọdún kristiẹni rí nínú wọn. Kò sì sí ẹnì kan nínú àwọn t’ó fi dáadáa tẹ̀lé wọn, t’ó lo gbólóhùn yìí fún sísọ oúnjẹ ọdún kristiẹni di ẹ̀tọ́. Tí ẹnì kan bá wá ń lo gbólóhùn náà fún jíjẹ oúnjẹ ọdún kristiẹni àti sísọ ọ́ di oúnjẹ ẹ̀tọ́, ó ti gbé gbólóhùn náà ka àyè tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) kò gbà lérò. Ó sì ti fi ara rẹ̀ hàn gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó gbọ́ àgbọ́yé āyah ju Òjíṣẹ́ Allāhu (sollalāhu 'alayhi wa sallam) àti àwọn Sọhābah rẹ̀ (r.ahm.) pẹ̀lú àwọn aṣíwájú rere fún wa (kí Allāhu kẹ́ gbogbo wọn). Síwájú sí i, àfàìmọ̀ kí ẹni tí ó bá ń ló gbólóhùn náà fún sísọ oúnjẹ ọdún àwọn kristiẹni di ẹ̀tọ́ fún àwa mùsùlùmí má sọra rẹ̀ di kèfèrí nítorí àwọn ewu ńlá t’ó rọ̀ mọ́ ọn. Àwọn ewu ńlá náà nìwọ̀nyí: Gbígbà tí àwọn kristiẹni gbàgbọ́ pé wọ́n kan olúwa àti olùgbàlà àwọn mọ́ igi àgbélébùú, tí ó sì kú sórí igi àgbélébùú náà, tí ó tún jí dìde l’ọ́jọ́ kẹta, l’ó mú wọn dá ọdún Àjíǹde Jésù Kristi sílẹ̀. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì sọ pé irọ́ ni wọ́n pa. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì fi òdodo ọ̀rọ̀ rinlẹ̀ pé ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) kì í ṣe olúwa àti olùgbàlà (sūrah al-Mọ̄’idah; 5:17 àti 75). Ó tún fi rinlẹ̀ pé wọn kò pa ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām), wọn kò sì kàn án mọ igi àgbélébùú (sūrah an-Nisā’; 4:157-158). Àti pé àwọn yẹhidi di kèfèrí nípasẹ̀ bí wọ́n ṣe pète pèrò láti mú ‘Īsā ọmọ Mọryamọ ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) kàn mọ́ igi àgbélébùú. Mùsùlùmí yó sì máa jẹ́ mùsùlùmí lórí gbígba ọ̀rọ̀ Allāhu gbọ́ ní òdodo. Tí irú mùsùlùmí yìí bá tún wá bá àwọn kristiẹni dá sí ọdún Àjíǹde Jésù, ó ti fara mọ́ ìgbàgbọ́ nínú ikú Jésù lórí igi àgbélébùú nìyẹn. Ó sì ti pe Allāhu ní òpùrọ́. Ẹ̀sìn rẹ̀ sì ti bàjẹ́ nípasẹ̀ bẹ́ẹ̀. Ẹ wo ewu ńlá tí oúnjẹ ọdún Àjíǹde Jésù bí fún mùsùlùmí! Bákan náà, àwọn kristiẹni ń ṣe ọdún kérésìmesì nítorí pé wọ́n gbàgbọ́ pé ọjọ́ yẹn ni wọ́n bí ọmọ Ọlọ́hun sáyé ní àwòrán ènìyàn. Wọ́n sì ń pè é ní Ọlọ́hun ọmọ. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì sọ pé ọ̀rọ̀ kò rí bẹ́ẹ̀. Allāhu sọ pé Òun kò bímọ, Òun kò sì fi ẹnì kan kan ṣe ọmọ. Bẹ́ẹ̀ sì ni pé, kò sí ọlọ́hun mẹta lọ́kan. Ọlọ́hun Olúwa àti Olùgbàlà, ẹyọ kan ṣoṣo l’Ó wà. Mùsùlùmí yó sì máa jẹ́ mùsùlùmí lórí gbígba ọ̀rọ̀ Allāhu gbọ́ ní òdodo. Tí irú mùsùlùmí yìí bá tún wá bá àwọn kristiẹni dá sí ọdún ọjọ́ ìbí ọlọ́hun ọmọ, ó ti fara mọ́ ìgbàgbọ́ pé Ọlọ́hun bímọ, ó sì ti fara mọ́ ìgbàgbọ́ nínú ọlọ́hun ọmọ. Nípa èyí, irú mùsùlùmí yìí ti pe Allāhu ní òpùrọ́. Ẹ̀sìn rẹ̀ sì ti bàjẹ́ nípasẹ̀ bẹ́ẹ̀. Ẹ wo ewu ńlá tí oúnjẹ ọdún kérésìmesì bí fún mùsùlùmí! Wòóore: Ìjẹkújẹ wulẹ̀ ni oúnjẹ ayẹyẹ ọjọ́ ìbí Ànábì tiwa gan-an, ìyẹn oúnjẹ mòlídì. Kí wá ni ó máa jẹ́ ìdájọ́ jíjẹ oúnjẹ ọjọ́ ìbí “ọlọ́hun ọmọ” bí kò ṣe èèwọ̀. Bákan náà, àwọn kristiẹni gbàgbọ́ pé oṣù ìbẹ̀rẹ̀ ọdún ni oṣù January.
Àwọn kristiẹni tún gbàgbọ́ pé oṣù ìparí ọdún ni oṣù December. Wọ́n sì sọ òru ìkẹ́yìn December di òru àìsùn àdúà. Wọ́n tún sọ ọjọ́ àkọ́kọ́ nínú oṣù January di ọjọ́ ọdún. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì sọ pé ọ̀rọ̀ kò rí bẹ́ẹ̀ rárá. Kò sí osù January, February títí dé December ní ọ̀dọ̀ Òun. Allähu (subhānahu wa ta'ālā) sì fi àwọn orúkọ oṣù tiRẹ̀ rinlẹ̀ fún wa. Ó ní orúkọ oṣù ìbẹ̀rẹ̀ ọdún ni oṣù Muharram. Orúkọ oṣù ìparí ọdún ni oṣù Thul-hijjah. Àti pé ìwádìí fi rinlẹ̀ pé àwọn orúkọ oṣù tí àwọn kristiẹni gbàgbọ́ nínú wọn wọ̀nyẹn kò jẹ́ kiní kan bí kò ṣe àwọn orúkọ àwọn òrìṣà òyìnbó. Bí àpẹẹrẹ, òrìṣà ìbẹ̀rẹ̀ àti ìdáwọ́lé kan tí àwọn òyìnbó abọ̀rìṣà ń pè ní Janus, ni wọ́n fi gbé oṣù àti ọdún January kalẹ̀. Àwọn kristiẹni sì tẹ́wọ́ gbà á lọ́wọ́ wọn. Mùsùlùmí yó sì máa jẹ́ mùsùlùmí lórí gbígba ọ̀rọ̀ Allāhu gbọ́ ní òdodo. Tí irú mùsùlùmí yìí bá tún wá bá àwọn kristiẹni dá sí ọdún January, ó ti fara mọ́ ìgbàgbọ́ nínú January títí dé December. Ó sì ti yọ́nú sí àwọn òrìṣà tí wọ́n fi sọrí àwọn orúkọ oṣù náà. Nípa èyí, irú mùsùlùmí bẹ́ẹ̀ ti pe Allāhu ní òpùrọ́. Ẹ̀sìn rẹ̀ sì ti bàjẹ́ nípasẹ̀ bẹ́ẹ̀. Ẹ wo ewu ńlá tí oúnjẹ ọdún January bí fún mùsùlùmí! Wòóore, àwa mùsùlùmí tí à ń ṣẹ̀mí ní orílẹ̀ èdè tí kò lo òfin ’Islām, kò ní ìlànà mìíràn fún ṣíṣí òǹkà ọjọ́ fún àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ ojoojúmọ́ wa àfi lílo àwọn orúkọ oṣù àwọn ọ̀ṣẹbọ wọ̀nyẹn. Èyí wà lábẹ́ làlúrí títí di ìgbà tí ìjọba t’ó máa lo òfin ’Islām máa fi dìde ní orílẹ̀ èdè wa. Àmọ́ èèwọ̀ ni fún wa láti dunnú sí lílo àwọn orúkọ oṣù àwọn abọ̀rìṣà náà. Ọ̀kan pàtàkì lára dídunú sí i ni ṣíṣe ọdún rẹ̀ nítorì pé ìdùnnú ní ọdún ṣíṣe. Ará ìjọ́sìn sì ni ọdún ṣíṣe wà pẹ̀lú. Ìjọbà kò sì jẹ ẹnikẹ́ni nípá láti ṣe ọdún kan kan, áḿbọ̀sìbọ́sí pé ṣíṣe ọdún January máa wọ ipò làlúrí fún àwa mùsùlùmí. Nítorí náà, gbólóhùn yìí “Àti oúnjẹ àwọn tí A fún ní tírà, ẹ̀tọ́ ni fun yín.” Kò fi ọ̀nà kan kan sọ oúnjẹ ọdún àwọn kristiẹni di ẹ̀tọ́ fún àwa mùsùlùmi. Àwọn oúnjẹ wọn tí kò jẹmọ́ ìsìn wọn, tàbí ẹran tí kristiẹni kò fi orúkọ Jésù pa nínú àwọn ẹran tí Allāhu ṣe jíjẹ rẹ̀ ní ẹ̀tọ́ fún àwa mùsùlùmí nìkan ni gbólóhùn náà ń tọ́ka sí.
2 Kíyè sí i, a rí nínú àwọn onímọ̀ ẹ̀sìn tí ó gbá ọ̀rọ̀ yìí mú bẹ́ẹ̀ láì ṣíjú wo àwọn āyah mìíràn t’ó rọ̀mọ́ ìgbéyàwó, láì sì ṣíjú wo àwọn ewu ńlá tí kò ṣe é jànìyàn t’ó tún rọ̀ mọ́ ìgbéyàwó. Dandan sì ni fún wa láti lo āyah papọ̀ mọ́ra wọn ní ọ̀nà tí kò fi níí já sí pé mùsùlùmí tẹ̀lé ìtúmọ̀ ojú-ọ̀rọ̀ nìkan ní ìyapa sí ìtúmọ̀ ojú ọ̀rọ̀ mìíràn. Ní àkọ́kọ́ ná, nínú sūrah al-Baƙọrah; 2:221, Allāhu ṣe é ní èèwọ̀ fún wa láti fẹ́ ọ̀ṣẹbọ àfi tí ó bá fi ẹbọ sílẹ̀. Kí sì ni ẹbọ ní àyè yìí bí kò ṣe jíjọ́sìn fún ẹ̀dá àti pípe ẹ̀dá lẹ́yìn Allāhu. Kí sì ni ẹ̀sìn kristiẹni bí kò ṣe jíjọ́sìn fún Jésù àti pípe Jésù lẹ́yìn Allāhu. Bákan náà, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) pa wá láṣẹ pé kí á ṣọ́ ara ilé wa níbi ìyà Iná, ìyẹn nínú sūrah at-Tahrīm; 66:6. Ta sì ni ará ilé wa bí kò ṣe àwọn ìyàwó àti àwọn ọmọ wa. Láti ọ̀dọ̀ ’Abū Huraerah (rọdiyallāhu 'anhu), Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sọ pé: “Kò sí ọmọ kan àfi kí wọ́n bí i sórí àdámọ́ ’Islām, àmọ́ àwọn òbí rẹ̀ ló máa sọ ọ́ di yẹhudi tàbí kristiẹni tàbí abọ̀rìṣà.” (Bukọ̄riy àti Muslim). Nítorí náà, ọ̀rọ̀ t’ó tẹ̀wọ̀n jùlọ, t’ó sì fọkàn balẹ̀ jùlọ ni pé, àwọn obìnrin kristiẹni tàbí yẹhudi t’ó bá gba ’Islām nìkan ni ọ̀rọ̀ yìí jẹmọ́. Ìkìlọ̀ t’ó sì parí āyah yìí gan ti fi hàn pé tí mùsùlùmí bá ti ipasẹ̀ jíjẹ oúnjẹ wọn tàbí ipasẹ̀ fífi wọ́n ṣe ìyàwó di kèfèrí, iṣẹ́ rẹ̀ máa bàjẹ́. Ó sì máa di ẹni òfò. Kí Allāhu kó wa yọ.


الصفحة التالية
Icon