Ẹ̀yin ahlul-kitāb, dájúdájú Òjíṣẹ́ Wa ti dé ba yín, tí ó ń ṣe àlàyé (ọ̀rọ̀) fun yín lẹ́yìn àsìkò tí A ti dá àwọn Òjísẹ́ dúró, nítorí kí ẹ má baà wí pé: “Kò sí oníròó ìdùnnú tàbí olùkìlọ̀ kan tí ó dé bá wa.” Nítorí náà, dájúdájú oníròó ìdùnnú àti olùkìlọ̀ kan ti dé ba yín. Allāhu sì ni Alágbára lórí gbogbo n̄ǹkan.


الصفحة التالية
Icon