Dájúdájú àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo àti àwọn yẹhudi, nasara àti àwọn sọ̄bi’u; ẹnikẹ́ni tí ó bá ní ìgbàgbọ́ òdodo nínú Allāhu àti Ọjọ́ Ìkẹ́yìn, tí ó sì ṣe iṣẹ́ rere, ẹ̀san wọn ń bẹ fún wọn ní ọ̀dọ̀ Olúwa wọn. Kò sí ìbẹ̀rù fún wọn. Wọn kò sì níí banújẹ́.
____________________
Irú āyah yìí tún wà nínú sūrah al-Mọ̄’idah; 5:69 àti sūrah al- Hajj; 22:17. Àgbọ́yé rẹ̀ sì ni pé, kí àwa mùsùlùmí dúró ṣínṣín nínú ẹ̀sìn ’Islām. Kí á sì mọ̀ pé dájúdájú kò sí ọ̀nà mìíràn fún àwọn yẹhudi, àwọn kristiẹni, àwọn mọjūs, àwọn sọ̄bi’u àti àwọn ọ̀ṣẹbọ bí kò ṣe ìgbàgbọ́ nínú Allāhu gẹ́gẹ́ bí àwa mùsùlùmí ṣe gbà Á gbọ́ àti ṣíṣe iṣẹ́ rere, tí í ṣe sunnah Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Èyí rí bẹ́ẹ̀ fún ìdí pàtàkì mẹ́ta. Ìkíní: Kò sí ẹ̀sìn kan lọ́dọ̀ Allāhu àfi ’Islām (Ẹ wo sūrah āli-’Imrọ̄n; 3:19, 85 àti sūrah al-Mọ̄’dah; 5:3.) Ìkejì: Kò sí Ànábì tàbí Òjíṣẹ́ kan tí Allāhu rán níṣẹ́ rí pẹ̀lú ẹ̀sìn mìíràn àfi ’Islām. (Ẹ wo sūrah al-Baƙọrah; 2:140 àti 213.) Ìkẹta: Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) pe ẹ̀sìn àwọn yẹhudi àti nasara ní ẹ̀sìn irọ́. (Ẹ wo sūrah at-Taobah; 9:29.) Bákan náà, láti ọ̀dọ̀ ’Abū Huraerah (rọdiyallāhu 'anhu), láti ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ Allāhu (sollalāhu 'alayhi wa sallam), dájúdájú Òjíṣẹ́ Allāhu sọ pé: “Èmi fi Ẹni tí ẹ̀mí Muhammad wà ní ọwọ́ Rẹ̀ búra; ẹnì kan nínú ìjọ yìí, yẹhudi tàbí nasara, kò níí gbọ́ nípa mi, lẹ́yìn náà kí ó kú láì gbàgbọ́ nínú ohun tí Wọ́n fi rán mi níṣẹ́, àfi kí ó jẹ́ ara èrò inú Iná.” (Muslim).


الصفحة التالية
Icon