Kí àwọn tí A fún ní ’Injīl ṣèdájọ́ pẹ̀lú ohun tí Allāhu sọ̀kalẹ̀ nínú rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣèdájọ́ pẹ̀lú ohun tí Allāhu sọ̀kalẹ̀, àwọn wọ̀nyẹn ni òbìlẹ̀jẹ́.
____________________
Kíyè sí i, bí àwọn tí A fún ní ’Injīl bá lò ó gẹ́gẹ́ bí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe sọ̀ ọ́ kalẹ̀, dandan ni fún wọn láti tẹ̀lé Ànábì àsìkò yìí, Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Nítorí pé, àsọtẹ́lẹ̀ nípa Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kúkú wà nínú rẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, nínú ìwé Johannu 1:19-21, bíbélì sọ pé: (19) Eyi si ni ẹri Johannu, nigba ti awọn Ju ran awọn alufa ati awọn ọmọ Lefi lati Jerusalẹmu wa lati bi i leere pe. Tani iwọ ṣe? (20) O si jẹwọ, ko si sẹ; o si jẹwọ pe. Emi ki i ṣe Kristi naa. (21) Wọn si bi i pe, Tani iwọ ha ṣe? Elijah ni ọ bi? O si wipe Bẹẹkọ, Iwọ ni woli naa bi “ẹni tí à ń retí”? O si dahun wipe, Bẹẹkọ. [Complete Jewish Bible àti New Living Translation Bible. Kíyè sí i, àwọn bíbélì yòókú ti yọ “ẹni tí à ń retí” kúrò gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn.] Nítorí irú àsọtẹ́lẹ̀ wọ̀nyí ló mú kí Waraƙọh ọmọ Naofal, ẹ̀bí ìyáwó àkọ́fẹ́ Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam), Kọdījah ọmọ Kuwaelid (rọdiyallāhu 'anhā), ṣe gbà pé òun máa tẹ̀lé Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) nígbàkígbà tí Allāhu bá rán an níṣẹ́ sí àwọn ènìyàn. Àmọ́ ó kú ṣíwájú àsìkò náà. Síwájú sí i, kàyéfì tí ń bẹ́ lára àwọn yẹ̀húdí àti nàsárá ni pé, wọ́n kò yé retí ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ náà. Kódà wọ́n máa ń fi bá àwọn ọ̀ṣẹbọ sọ̀rọ̀ nínú ìwàásù wọn fún wọn. Àmọ́ nígbà tí àsọtẹ́lẹ̀ náà wá sí ìmúṣẹ, ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ wọn l’ó gbúnrí. Wọ́n sì ṣàì gbàgbọ́ nínú Ànábì náà (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ti sọ nípa èyí nínú sūrah al-Baƙọrah; 2:89.


الصفحة التالية
Icon