Tí ó bá jẹ́ pé dájúdájú wọ́n lo at-Taorāh àti al-’Injīl àti ohun tí A sọ̀kalẹ̀ fún wọn láti ọ̀dọ̀ Olúwa wọn (ìyẹn, al-Ƙur’ān), wọn ìbá máa jẹ láti òkè wọn àti láti ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ wọn. Ìjọ kan ń bẹ nínú wọn t’ó dúró déédé, (àmọ́) ohun tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wọn ń ṣe níṣẹ́ burú.
____________________
Ọ̀wọ́ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ìpèpè Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) dé bá láyé, tí wọ́n sì gbàgbọ́ nínú rẹ̀ (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Wọ́n sì gba ’Islām. Èyí wà ní ìbámu sí sūrah al-Mọ̄’idah; 5:82-86 àti sūrah āl-‘Imrọ̄n; 3:113 àti 115.


الصفحة التالية
Icon