Nígbà tí wọ́n bá sọ fún wọn pé: “Ẹ máa bọ̀ wá síbi ohun tí Allāhu sọ̀kalẹ̀. (Ẹ máa bọ̀ wá) sí ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ náà.” Wọ́n á wí pé: “Ohun tí a bá àwọn bàbá wa lórí rẹ̀ ti tó wa.” Ṣé pẹ̀lú bí ó ṣe jẹ́ pé àwọn bàbá wọn kò nímọ̀ kan kan, tí wọn kò sì mọ̀nà?
____________________
Ìyẹn nígbà tí Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) wà nílé ayé ṣíwájú kí ó tó kú. Àmọ́ lẹ́yìn ikú rẹ̀ (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kò sí àǹfààní fún ẹnikẹ́ni mọ́ láti kó ẹjọ́ lọ bá a nídìí sàréè rẹ̀. Nítorí náà, ní àsìkò tiwa yìí gbígbé ẹjọ́ lọ sí ilé-ẹjọ́ Ṣẹria ’Islām àti ọ̀dọ̀ àwọn onímọ̀ ’Islām tí wọ́n jẹ́ onisunnah lọ̀rọ̀ kàn. Èyí sì ni àgbọ́yé āyah náà. Ẹ tún wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah an-Nisā’; 4:64 àti sūrah āli-’Imrọ̄n; 3:101.


الصفحة التالية
Icon