Má ṣe lé àwọn t’ó ń pe Olúwa wọn ní òwúrọ̀ àti ní àṣálẹ́ dànù; wọ́n ń fẹ́ Ojú rere Rẹ̀ ni. Ìṣirò-iṣẹ́ wọn kò sí ní ọrùn rẹ ní ọ̀nà kan kan. Kò sì sí ìṣirò-iṣẹ́ tìrẹ náà ní ọrùn wọn ní ọ̀nà kan kan. Tí o bá lé wọn dànù, o sì máa wà nínú àwọn alábòsí.
____________________
Āyah yìí ń sọ nípa àwọn Sọhābah (r.ahm.) tí wọ́n jẹ́ tálíkà pọ́nńbélé, gẹ́gẹ́ bí āyah 53 tí ó tẹ̀lé āyah yìí ṣe fi hàn. Àwọn Sọhābah wọ̀nyí kò sì ní ibi iṣẹ́ kan kan tí wọ́n lè máa rí lọ. Gbàgede mọ́sálásí Òjíṣẹ́ (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ni ibùgbé àti ibùsùn wọn. Gbàgede mọ́sálásí yìí ni à ń pè ní suffah. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe àwọn Sọhābah wọ̀nyí ní ahlu-ssuffah "ará gbàgede". Wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu nínú oúnjẹ ọrẹ tí àwọn t’ó ríbi lọ bá gbé wá fún Òjíṣẹ́ Allāhu (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Wọn a sì máa gbé sàárà fún wọn pẹ̀lú. Fún wí pé wọn kì í lọ sí ibì kan kan ló fi jẹ́ pé ní òwúrọ̀ àti ní àṣálẹ́ ṣíṣe tilāwa al-Ƙur’ān àti ṣíṣe gbólóhùn athikir tí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kọ́ wọn ni àwọn Sọhābah wọ̀nyí dúnnímọ́ jùlọ. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì pa Ànábì Rẹ̀ ní àṣẹ láti máa wà pẹ̀lú wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe máa ń wà pẹ̀lú àwọn mìíràn tí wọ́n ń ríbi lọ fún ọ̀nà ìjẹ-ìmu wọn. Nítorí náà, àwọn Sọhābah wọ̀nyí kì í ṣe sūfi. Wọn kì í sì ṣe onitọrīkọ kan kan. Irúfẹ́ āyah yìí tún wà nínú sūrah al-Kahf; 18:28.