Ṣé n̄ǹkan mìíràn ni kí n̄g wá ní olùdájọ́ lẹ́yìn Allāhu ni? Òun sì ni Ẹni tí Ó sọ Tírà kalẹ̀ fun yín tí wọ́n fi ṣàlàyé ìdájọ́. Àwọn tí A sì fún ní tírà mọ̀ pé, dájúdájú wọ́n sọ̀ ọ́ kalẹ̀ pẹ̀lú òdodo láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ. Nítorí náà, o ò gbọdọ̀ wà lára àwọn oníyèméjì.
____________________
Irú gbólóhùn yìí wà nínú sūrah Yūsuf; 12:111 àti sūrah an-Nahl; 16:89. Wàyí, àwọn n̄nkan titun titun àti àwọn n̄ǹkan ìgbàlódé t’ó ń ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn al-Ƙur’ān, tí Allāhu kò sì sọ̀rọ̀ nípa wọn ńkọ́? Kíyè sí i, al-Ƙur’ān dúró fún òṣùwọ̀n (fọ́múlà) àti ìdájọ́ tí a ó fi máa ṣe ìyàtọ̀ láààrin ìmọ̀ àti ìròrí, ohun rere àti aburú, ẹ̀tọ́ àti èèwọ̀, ìjọ́sìn àti ìranù, ìtẹ̀lé àṣẹ àti ìyapa àṣẹ, iṣẹ́ Ọgbà Ìdẹ̀ra àti iṣẹ́ Iná. Sunnah Ànábì wa Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sì dúró fún àlàyé al-Ƙur’ān.


الصفحة التالية
Icon