Sọ pé: "Èmi kò rí nínú ohun tí Wọ́n fi ránṣẹ́ sí mi tí Wọ́n ṣe jíjẹ rẹ̀ ní èèwọ̀ fún ẹni tí ó ń jẹ ẹ́ àfi ohun tí ó bá jẹ́ ẹran òkúǹbete tàbí ẹ̀jẹ̀ ṣíṣàn,1 tàbí ẹran ẹlẹ́dẹ̀ nítorí pé dájúdájú ẹ̀gbin ni, tàbí ẹran ìyapa (àṣẹ Allāhu) tí wọ́n pa pẹ̀lú orúkọ t’ó yàtọ̀ sí Allāhu. Nítorí náà, ẹnikẹ́ni tí ìnira (ebi) bá mú jẹ ẹ́, yàtọ̀ sí ẹni t’ó ń wá èèwọ̀ kiri àti olùtayọ-ẹnu-àlà, dájúdájú Olúwa rẹ ni Aláforíjìn, Àṣàkẹ́-ọ̀run.2
____________________
1 Láti ọ̀dọ̀ ọmọ ‘Umọr, láti ọ̀dọ̀ Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam), ó sọ pé: "A ṣe òkúǹbete méjì àti ẹ̀jẹ̀ méjì ní ẹ̀tọ́ fún wa; òkúǹbete méjì náà ni ẹja àti tata. Ẹ̀jẹ̀ méjì náà –mo rò ó sí pé Ànábì sọ pé- ẹ̀dọ̀ àti àwọ́n" (Sunanul-Baehaƙiy al-Kubrọ̄; 18776) 2 Āyah yìí kò kó gbogbo ohun jíjẹ àti ohun mímu t’ó jẹ́ harām sínú tán nítorí pé Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) kàn fi fọ èsì sí èrò-ọkàn àwọn ọ̀ṣẹbọ ni, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe jẹyọ ṣíwájú nínú āyah 138-139.