Àwọn t’ó ń ṣe sìná nínú àwọn obìnrin yín, ẹ wá ẹlẹ́rìí mẹ́rin nínú yín tí ó máa jẹ́rìí lé wọn lórí. Tí wọ́n bá jẹ́rìí lé wọn lórí, kí ẹ dè wọ́n mọ́ inú ilé títí ikú yóò fi pa wọ́n tàbí (títí) Allāhu yóò fi fún wọn ní ọ̀nà (mìíràn).
Èyí ni òfin àkọ́kọ́ lórí ìdíyàjẹ onísìná obìnrin. Lẹ́yìn náà, òfin lílẹ onísìná lókò pa dé lórí ẹni tí ó bá ṣe sìná lẹ́yìn tí ó ti ṣe nikāh rí. Èyí sì ni ọ̀nà mìíràn tí Allāhu fún wọn láti fi bá abilékọ t’ó ṣe sìná wí. Òfin àkọ́kọ́ yẹn ni àwọn kògbédè-ó-gbékèé ń lò fún ẹ̀há (hijāb) àwọn obìnrin mùsùlùmí, tí ó sì jẹ́ pé ọ̀tọ̀ ni āyah ìdíyàjẹ onísìná bí tinú sūrah an-Nūr; 24:2, ọ̀tọ̀ sì ni āyah ẹ̀há (hijāb) bí tinú sūrah an-Nūr; 24:31 àti sūrah al-’Ahzāb; 33:59.
الترجمة اليورباوية