ﯽ
                    surah.translation
            .
            
    
                                    من تأليف: 
                                            أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
                                                            .
                                                
            ﰡ
                                                                                                                
                                    ﭑﭒ
                                    ﰀ
                                                                        
                    (Ànábì s.a.w.) fajú ro, ó sì pẹ̀yìn dà
                                                                        nítorí pé afọ́jú wá bá a.
                                                                        Kí sì l’ó máa fi mọ̀ ọ́ pé ó ṣeé ṣe kí ó ṣàfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́)
                                                                        tàbí kí ó gbọ́ ìrántí, kí ìrántí náà sì ṣe é ní àǹfààní?
                                                                        Ní ti ẹni tí ó ka ara rẹ̀ kún ọlọ́rọ̀,
                                                                        òun ni ìwọ tẹ́tí sí.
                                                                        Kò sì sí ẹ̀ṣẹ̀ fún ọ bí kò bá ṣe àfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́).
                                                                        Ní ti ẹni tí ó sì wá bá ọ, t’ó ń yára gágá (sí ìrántí, ìyẹn afọ́jú), 
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﭴﭵ
                                    ﰈ
                                                                        
                    tí ó sì ń páyà (Allāhu), 
                                                                        ìwọ kò sì kọbi ara sí i. 
                                                                        Rárá (kò tọ́ bẹ́ẹ̀). Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
                                                                        Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó rántí rẹ̀.
                                                                        (Al-Ƙur’ān) wà nínú àwọn tàkádà alápọ̀n-ọ́nlé,
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﮇﮈ
                                    ﰍ
                                                                        
                    A gbé e ga, A sì ṣe é ní mímọ́
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﮊﮋ
                                    ﰎ
                                                                        
                    ní ọwọ́ àwọn òǹkọtíà (ìyẹn, àwọn mọlāika), 
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﮍﮎ
                                    ﰏ
                                                                        
                    àwọn alápọ̀n-ọ́nlé, àwọn ẹni rere.
                                                                        Wọ́n ti fi ènìyàn gégùn-ún (nípa) bí ó ṣe jẹ́ aláìmoore jùlọ!
                                                                        Kí sì ni Allāhu fi ṣẹ̀dá rẹ̀?
                                                                        Nínú àtọ̀ l’Ó ti ṣẹ̀dá rẹ̀. Ó sì pèbùbù (ẹ̀yà-ara) rẹ̀.
                                                                        Lẹ́yìn náà, Ó ṣe ọ̀nà àtiwáyé ní ìrọ̀rùn fún un.
                                                                        Lẹ́yìn náà, Ó máa pa á. Ó sì máa fi sínú sàréè.
                                                                        Lẹ́yìn náà, nígbà tí Allāhu bá fẹ́, Ó máa gbé e dìde.
                                                                        Ẹ gbọ́, ènìyàn kò tí ì ṣe n̄ǹkan tí Allāhu pa láṣẹ fún un. 
                                                                        Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí oúnjẹ rẹ̀.
                                                                        Dájúdájú Àwa ń rọ òjò ní púpọ̀. 
                                                                        Lẹ́yìn náà, A mú ilẹ̀ sán kànkàn. 
                                                                        A sì mú kóró èso hù jáde láti inú rẹ̀;
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﯦﯧ
                                    ﰛ
                                                                        
                    àti èso àjàrà àti kànnáfùrù,
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﯩﯪ
                                    ﰜ
                                                                        
                    àti igi òróró Zaetūn àti dàbínù, 
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﯬﯭ
                                    ﰝ
                                                                        
                    àti àwọn ọgbà t’ó kún fún igi, 
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﯯﯰ
                                    ﰞ
                                                                        
                    àti àwọn èso (mìíràn) pẹ̀lú ewé tí ẹranko ń jẹ, (A mú wọn hù jáde).
                                                                        (Wọ́n jẹ́ n̄ǹkan) ìgbádùn fún ẹ̀yin àti àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
                                                                        Nígbà tí fífọn sínú ìwo nígbà kejì bá ṣẹlẹ̀,
                                                                        ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò sá fún arákùnrin rẹ̀,
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﰀﰁ
                                    ﰢ
                                                                        
                    àti ìyá rẹ̀ pẹ̀lú bàbá rẹ̀,
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﰃﰄ
                                    ﰣ
                                                                        
                    àti ìyàwó rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀.
                                                                        Ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn ní ọjọ́ yẹn l’ó ti ní ọ̀ràn t’ó máa tó o ó rán. 
                                                                        Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn yóò mọ́lẹ̀.
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﰑﰒ
                                    ﰦ
                                                                        
                    Wọn yó máa rẹ́rìn-ín, wọn yó sì máa dunnú.
                                                                        Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn ni eruku yó sì bò mọ́lẹ̀.
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﭑﭒ
                                    ﰨ
                                                                        
                    Òkùnkùn yó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀.
                                                                        Àwọn wọ̀nyẹn, àwọn ni aláìgbàgbọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.