ﰍ
                    surah.translation
            .
            
    
                                    من تأليف: 
                                            أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
                                                            .
                                                
            ﰡ
Ké (al-Ƙur’ān) pẹ̀lú orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá.
                                                                        Ó ṣẹ̀dá ènìyàn láti ara ẹ̀jẹ̀ dídì.
                                                                        Ké e. Olúwa rẹ ni Alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ.
                                                                        Ẹni tí Ó fi ìmọ̀ nípa gègé ìkọ̀wé mọ ènìyàn.
                                                                        Ó fi ìmọ̀ tí ènìyàn kò mọ̀ mọ̀ ọ́n.
                                                                        Ní ti òdodo, dájúdájú ènìyàn kúkú ń tayọ ẹnu-àlà
                                                                        nítorí pé ó ríra rẹ̀ ní ọlọ́rọ̀. 
                                                                        Dájúdájú ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni àbọ̀ ẹ̀dá.
                                                                        Sọ fún mi nípa ẹni t’ó ń kọ̀
                                                                        fún ẹrúsìn kan nígbà tí (ẹrúsìn náà) kírun!
                                                                        Sọ fún mi (nípa ẹ̀san rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó wà lórí ìmọ̀nà (’Islām)
                                                                        tàbí pé ó pàṣẹ ìbẹ̀rù (Allāhu)!
                                                                        Sọ fún mi (nípa ìyà rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó pe òdodo nírọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i?
                                                                        Ṣé kò mọ̀ pé dájúdájú Allāhu ń rí (òun ni?)
                                                                        Bẹ́ẹ̀ ni (Allāhu ń rí i.) Dájúdájú tí kò bá jáwọ́ (níbi dídí i lọ́wọ́), dájúdájú A máa fi àásó orí rẹ̀ wọ́ ọ (sínú Iná);
                                                                        àásó orí òpùrọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﭧﭨ
                                    ﰐ
                                                                        
                    Nítorí náà, kí ó pe àwọn olùbájókòó rẹ̀.
                                                                        
                                                                                                                
                                    ﭪﭫ
                                    ﰑ
                                                                        
                    Àwa máa pe àwọn mọlāika ẹ̀ṣọ́ Iná.
                                                                        Rárá o, má ṣe tẹ̀lé tirẹ̀. Forí kanlẹ̀ (kí o kírun), kí o súnmọ́ (Allāhu).