ترجمة معاني سورة الحاقة باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
آية رقم 1
ﮯ
ﮰ
Ìṣẹ̀lẹ̀ Òdodo
آية رقم 2
ﮱﯓ
ﯔ
Kí ni Ìṣẹ̀lẹ̀ Òdodo.
آية رقم 3
ﯕﯖﯗﯘ
ﯙ
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Ìṣẹ̀lẹ̀ Òdodo?
آية رقم 4
ﯚﯛﯜﯝ
ﯞ
Àwọn ìjọ Thamūd àti ìjọ ‘Ād pe Ìpáyà nírọ́.
Nínú àwọn orúkọ fún Ọjọ́ Àjíǹde ni Ìṣẹ̀lẹ̀ Òdodo àti Ìpáyà.
آية رقم 5
ﯟﯠﯡﯢ
ﯣ
Ní ti ìjọ Thamūd, wọ́n fi igbe t’ó tayọ ẹnu-àlà pa wọ́n rẹ́.
آية رقم 6
ﯤﯥﯦﯧﯨﯩ
ﯪ
Ní ti ìjọ ‘Ād, wọ́n fi atẹ́gùn líle t’ó tayọ ẹnu-àlà pa wọ́n rẹ́.
آية رقم 7
Ó dẹ ẹ́ sí wọn fún òru méje àti ọ̀sán mẹ́jọ láì dáwọ́ dúró. O sì máa rí ìjọ náà tí wọ́n ti kú sínú rẹ̀ bí ẹni pé kùkùté igi dàbínù t’ó ti luhò nínú ni wọ́n.
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah Fussilat; 41:16.
آية رقم 8
ﯼﯽﯾﯿﰀ
ﰁ
Ǹjẹ́ o rí ẹnì kan nínú wọn t’ó ṣẹ́ kù bí?
آية رقم 9
ﭑﭒﭓﭔﭕﭖ
ﭗ
Fir‘aon àti àwọn t’ó ṣíwájú rẹ̀ àti àwọn ìlú tí wọ́n dojú rẹ̀ bolẹ̀ dé pẹ̀lú àwọn àṣìṣe.
آية رقم 10
ﭘﭙﭚﭛﭜﭝ
ﭞ
Wọ́n yapa Òjíṣẹ́ Olúwa wọn. Ó sì gbá wọn mú ní ìgbámú àlékún.
آية رقم 11
Dájúdájú nígbà tí omi tayọ ẹnu-àlà. A gbe yín gun ọkọ̀ ojú-omi.
آية رقم 12
ﭧﭨﭩﭪﭫﭬ
ﭭ
Nítorí kí Á lè fi ṣe ìrántí fun yín àti nítorí kí etí t’ó ń ṣọ́ n̄ǹkan lè ṣọ́ ọ.
آية رقم 13
ﭮﭯﭰﭱﭲﭳ
ﭴ
Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún ikú ní fífọn ẹyọ kan,
آية رقم 14
ﭵﭶﭷﭸﭹﭺ
ﭻ
tí wọ́n gbé ilẹ̀ àti àpáta sókè, tí wọ́n sì rún méjèèjì wómúwómú ní rírún ẹ̀ẹ̀ kan,
آية رقم 15
ﭼﭽﭾ
ﭿ
ní ọjọ́ yẹn ni Ìṣẹ̀lẹ̀ máa ṣẹlẹ̀.
آية رقم 16
ﮀﮁﮂﮃﮄ
ﮅ
Àti pé sánmọ̀ yó fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Ó sì máa fúyẹ́ gẹgẹ ní ọjọ́ yẹn.
آية رقم 17
Àwọn mọlāika sì máa wà ní àwọn ẹ̀gbẹ́ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àti pé ní ọjọ́ yẹn, lókè wọn, àwọn (mọlāika) mẹ́jọ ni wọ́n máa ru Ìtẹ́ Olúwa rẹ.
آية رقم 18
ﮑﮒﮓﮔﮕﮖ
ﮗ
Ní ọjọ́ yẹn, wọn yóò máa ṣẹ́rí yín wá (fún ìṣírò-iṣẹ́). Kò sì níí sí àṣírí yín kan t’ó máa pamọ́ (fún Wa).
آية رقم 19
Nítorí náà, ní ti ẹni tí wọ́n bá fún ní tírà rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, ó máa sọ pé: "Ẹ gbà, ẹ ka tírà mi.
آية رقم 20
ﮢﮣﮤﮥﮦ
ﮧ
Dájúdájú èmi ti mọ àmọ̀dájú pé dájúdájú èmi yóò bá ìṣírò-iṣẹ́ mi pàdé."
آية رقم 21
ﮨﮩﮪﮫ
ﮬ
Nítorí náà, ó máa wà nínú ìṣẹ̀mí t’ó máa yọ́nú sí
آية رقم 22
ﮭﮮﮯ
ﮰ
nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra gíga.
آية رقم 23
ﮱﯓ
ﯔ
Àwọn èso rẹ̀ (sì) wà ní àrọ́wọ́tó.
آية رقم 24
Ẹ jẹ, kí ẹ sì mu pẹ̀lú ìgbàdún nítorí ohun tí ẹ tì síwájú nínú àwọn ọjọ́ tí ó ti ré kọjá.
آية رقم 25
Ní ti ẹni tí wọ́n bá sì fún ní tírà rẹ̀ ní ọwọ́ òsì rẹ̀, ó máa wí pé: "Háà! Kí wọ́n sì má fún mi ni tírà mi!
Àwọn kristiẹni sọ pé, “Āyah yìí ń sọ pé ọwọ́ òsì ni àwọn aláìgbàgbọ́ máa fi gba ìwé iṣẹ́ wọn, àmọ́ sūrah al-’Inṣiƙọ̄ƙ; 84:10 ń sọ pé láti ẹ̀yìn ni wọ́n máa ti gbà á.” Wọ́n ní, “Ìtakora nìyẹn!”
Èsì: Ìtakora tófẹ́jọbẹ́ẹ̀ ni, kì í ṣe ìtakora tóríbẹ́ẹ̀. Àlàyé rẹ̀ nìyí, méjéèjì ló máa ṣẹlẹ̀ sí wọn nítorí pé, ọwọ́ òsì ni aláìgbàgbọ́ máa tì bọ inú igbá-àyà rẹ̀ bọ́ sí ẹ̀yìn rẹ̀ láti fi gba ìwé iṣẹ́ rẹ̀.
Èsì: Ìtakora tófẹ́jọbẹ́ẹ̀ ni, kì í ṣe ìtakora tóríbẹ́ẹ̀. Àlàyé rẹ̀ nìyí, méjéèjì ló máa ṣẹlẹ̀ sí wọn nítorí pé, ọwọ́ òsì ni aláìgbàgbọ́ máa tì bọ inú igbá-àyà rẹ̀ bọ́ sí ẹ̀yìn rẹ̀ láti fi gba ìwé iṣẹ́ rẹ̀.
آية رقم 26
ﯩﯪﯫﯬ
ﯭ
Àti pé èmi kò mọ ohun tí ìṣírò-iṣẹ́ mi jẹ́.
آية رقم 27
ﯮﯯﯰ
ﯱ
Háà! Kí ikú sì jẹ́ òpin (ọ̀rọ̀ ẹ̀dá).
آية رقم 28
ﯲﯳﯴﯵﯶ
ﯷ
Dúkìá mi kò sì rọ̀ mí lọ́rọ̀.
آية رقم 29
ﯸﯹﯺ
ﯻ
Agbára mi sì ti parun."
آية رقم 30
ﯼﯽ
ﯾ
Ẹ mú un, kí ẹ dè é ní ọwọ́ mọ́ ọrùn.
آية رقم 31
ﯿﰀﰁ
ﰂ
Lẹ́yìn náà, inú iná Jẹhīm ni kí ẹ mú un wọ̀.
آية رقم 32
Lẹ́yìn náà, inú ẹ̀wọ̀n tí gígùn rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin gígùn thar‘u ni kí ẹ kì í sí.
Gígùn “Thar‘u” kan ni gígùn láti ìlú Mọkkah sí ibi tí ó jìnnà jùlọ sí ìlú Mọkkah.
آية رقم 33
ﰋﰌﰍﰎﰏﰐ
ﰑ
Dájúdájú òun kì í gbàgbọ́ nínú Allāhu, Atóbi.
آية رقم 34
ﰒﰓﰔﰕﰖ
ﰗ
Kì í sì gba ènìyàn níyànjú láti bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.
آية رقم 35
ﰘﰙﰚﰛﰜ
ﰝ
Nítorí náà, kò níí sí ọ̀rẹ́ ìmùlẹ̀ kan fún un níbí yìí ní òní.
آية رقم 36
ﭑﭒﭓﭔﭕ
ﭖ
Kò sì níí sí oúnjẹ kan (fún un) bí kò ṣe (oúnjẹ) àwọyúnwẹ̀jẹ̀.
آية رقم 37
ﭗﭘﭙﭚ
ﭛ
Kò sí ẹni tí ó máa jẹ ẹ́ bí kò ṣe àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
آية رقم 38
ﭜﭝﭞﭟ
ﭠ
Nítorí náà, Èmi ń búra pẹ̀lú ohun tí ẹ̀ ń fojú rí
آية رقم 39
ﭡﭢﭣ
ﭤ
àti ohun tí ẹ ò fojú rí.
آية رقم 40
ﭥﭦﭧﭨ
ﭩ
Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ọ̀rọ̀ (tí A fi rán) Òjíṣẹ́, alápọ̀n-ọ́nlé.
“Ọ̀rọ̀ òjíṣẹ́” ni ìtúmọ̀ “ƙọolu rọsūl, àmọ́ al-Ƙur’ān kì í ṣe ọ̀rọ̀ Òjíṣẹ́ bí kò ṣe “Ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun”. Àgbékalẹ̀ irúfẹ́ ọ̀rọ̀ yìí ni ṣíṣe àfitì ọ̀rọ̀ sí ọ̀dọ̀ alágbàsọ. Bákan náà, āyah yìí jọ āyah 19 nínú sūrah at-Tẹkwīr ní ìsọ, àmọ “Òjíṣẹ́” tí wọ́n gbàlérò nínú āyah ti sūrah al-Hāƙƙọh ni Òjíṣẹ́ abara, ìyẹn Ànábì wa Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam), Òjíṣẹ́ mọlāika ni wọ́n sì gbàlérò nínú āyah ti sūrah at-Tẹkwīr. Sàkánì ti ìkọ̀ọ̀kan ti jẹyọ l’ó ṣàfi hàn èyí bẹ́ẹ̀.
آية رقم 41
Kì í ṣe ọ̀rọ̀ eléwì. Ohun tí ẹ gbàgbọ́ kéré púpọ̀.
آية رقم 42
Kì í sì ṣe ọ̀rọ̀ adábigba. Díẹ̀ lẹ̀ ń lò nínú ìrántí.
آية رقم 43
ﭻﭼﭽﭾ
ﭿ
Wọ́n sọ̀ ọ́ kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
آية رقم 44
ﮀﮁﮂﮃﮄ
ﮅ
Tí ó bá jẹ́ pé (Ànábì) dá àdápa apá kan ọ̀rọ̀ náà mọ́ Wa ni,
آية رقم 45
ﮆﮇﮈ
ﮉ
Àwa ìbá gbá a mú lọ́wọ́ ọ̀tún.
آية رقم 46
ﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
Lẹ́yìn náà, Àwa ìbá já isan ọrùn rẹ̀.
آية رقم 47
ﮏﮐﮑﮒﮓﮔ
ﮕ
Kò sì sí ẹnì kan nínú yín tí ó máa gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ (Wa).
آية رقم 48
ﮖﮗﮘ
ﮙ
Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni ìrántí fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).
آية رقم 49
ﮚﮛﮜﮝﮞ
ﮟ
Dájúdájú Àwa sì mọ̀ pé àwọn t’ó ń pe al-Ƙur’ān nírọ́ wà nínú yín.
آية رقم 50
ﮠﮡﮢﮣ
ﮤ
Dájúdájú al-Ƙur’ān máa jẹ́ àbámọ̀ fún àwọn aláìgbàgbọ́.
آية رقم 51
ﮥﮦﮧ
ﮨ
Dájúdájú al-Ƙur’ān ni òdodo t’ó dájú.
آية رقم 52
ﮩﮪﮫﮬ
ﮭ
Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa Rẹ, Atóbi.
تقدم القراءة