ترجمة معاني سورة الأعلى باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
آية رقم 1
ﮟﮠﮡﮢ
ﮣ
Ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni gíga jùlọ.
آية رقم 2
ﮤﮥﮦ
ﮧ
Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá. Ó sì ṣe (oríkèé-ríkèé rẹ̀) ní dọ́gbadọ́gba.
آية رقم 3
ﮨﮩﮪ
ﮫ
Ẹni tí Ó yan kádàrá (fún ẹ̀dá). Ó sì tọ́ ọ sọ́nà.
Nínú āyah yìí, mẹ́ta gbòòrò ni ìtọ́sọ́nà náà èyí tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ń ṣe fún àwa ènìyàn àti àlùjànnú. Ìkíní: ìtọ́sọ́nà ẹ̀sìn ’Islām. Nítorí ìtọ́sọ́nà yìí gan-an ni Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe sọ àwọn Tírà Rẹ̀ kalẹ̀, tí Ó sì gbé àwọn Òjíṣẹ́ Rẹ̀ dìde sí wa. Ìkejì: ìtọ́sọ́nà ẹ̀rí-ọkàn. Nípa èyí ni a fi mọ ohun rere àti ohun burúkú ní ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Ìfirinlẹ̀ rẹ̀ sì ń jẹyọ nínú àwọn tírà sánmọ̀ àti nínú ọ̀rọ̀ àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu (a.s.w.).
Ìkẹta: ìtọ́sọ́nà òye àtinúwá. Nípa èyí ni a ṣe ń ṣàmúlò àwọn ohun àmúṣọrọ̀ fún ìgbáyé-gbádùn. Ìtọ́sọ́nà yìí kò sì sọ ẹnikẹ́ni di Òjíṣẹ́ Allāhu. Tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá rí ìtọ́sọ́nà ẹ̀sìn ’Islām nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀, kò sí ẹ̀san rere kan fún un lórí rẹ̀ ní ọ̀run. Ó kàn wúlò dànù fún ayé ni.
Ìkẹta: ìtọ́sọ́nà òye àtinúwá. Nípa èyí ni a ṣe ń ṣàmúlò àwọn ohun àmúṣọrọ̀ fún ìgbáyé-gbádùn. Ìtọ́sọ́nà yìí kò sì sọ ẹnikẹ́ni di Òjíṣẹ́ Allāhu. Tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá rí ìtọ́sọ́nà ẹ̀sìn ’Islām nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀, kò sí ẹ̀san rere kan fún un lórí rẹ̀ ní ọ̀run. Ó kàn wúlò dànù fún ayé ni.
آية رقم 4
ﮬﮭﮮ
ﮯ
Ẹni tí Ó mú koríko tútù (hù) jáde,
آية رقم 5
ﮰﮱﯓ
ﯔ
Ó sì sọ ọ́ di gbígbẹ t’ó dúdú.
آية رقم 6
ﯕﯖﯗ
ﯘ
Àwa yóò máa ké (al-Ƙur’ān) fún ọ. Ìwọ kò sì níí gbàgbé.
آية رقم 7
Àyàfi ohun tí Allāhu bá fẹ́. Dájúdájú Ó mọ gban̄gba àti ohun t’ó pamọ́.
Ìyẹn nípasẹ̀ fífí ìdájọ́ kan pa ìdájọ́ t’ó ṣíwájú rẹ̀ rẹ́. Ẹ wo sūrah al-Baƙọrah; 2:106.
آية رقم 8
ﯤﯥ
ﯦ
Àwa yó sì ṣe iṣẹ́ rere ní ìrọ̀rùn fún ọ.
آية رقم 9
ﯧﯨﯩﯪ
ﯫ
Nítorí náà, ṣèrántí ní àyè tí ìrántí ti wúlò.
Ìyẹn ni pé, wọ́n fẹ́ kí ṣíṣe ìrántí ọ̀rọ̀ Allāhu jìnnà sí àyè ìhunrírà (bí ilé ọtí), ilé eré àti ilé awàdà nítorí pé, àwọn ènìyàn t’ó wà níbẹ̀ kò níí kọbi ara sí olùsọ̀rọ̀. Āyah yìí jọ sūrah an-Nisā’; 4:140 àti sūrah al-’Ani‘ām; 6:68.
آية رقم 10
ﯬﯭﯮ
ﯯ
Ẹni tí ó máa páyà (Allāhu) máa lo ìrántí.
آية رقم 11
ﭑﭒ
ﭓ
Olórí-burúkú sì máa takété sí i.
آية رقم 12
ﭔﭕﭖﭗ
ﭘ
(Òun sì ni) ẹni tí ó máa wọ inú Iná t’ó tóbi.
آية رقم 13
ﭙﭚﭛﭜﭝﭞ
ﭟ
Lẹ́yìn náà, kò níí kú sínú rẹ̀, kò sì níí ṣẹ̀mí (àlàáfíà).
آية رقم 14
ﭠﭡﭢﭣ
ﭤ
Dájúdájú ẹni tí ó bá ṣàfọ̀mọ́ (ọkàn rẹ̀) ti jèrè.
آية رقم 15
ﭥﭦﭧﭨ
ﭩ
Ó tún rántí orúkọ Olúwa rẹ̀, ó sì kírun.
آية رقم 16
ﭪﭫﭬﭭ
ﭮ
Rárá, ńṣe l’ẹ̀ ń gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé.
آية رقم 17
ﭯﭰﭱ
ﭲ
Ọ̀run sì lóore jùlọ, ó sì máa wà títí láéláé.
آية رقم 18
ﭳﭴﭵﭶﭷ
ﭸ
Dájúdájú èyí wà nínú àwọn tákàdá àkọ́kọ́,
آية رقم 19
ﭹﭺﭻ
ﭼ
tákàdá (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm àti (Ànábì) Mūsā.
تقدم القراءة