سورة عبس

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني سورة عبس باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

آية رقم 1
(Ànábì s.a.w.) fajú ro, ó sì pẹ̀yìn dà
آية رقم 2
nítorí pé afọ́jú wá bá a.
آية رقم 3
Kí sì l’ó máa fi mọ̀ ọ́ pé ó ṣeé ṣe kí ó ṣàfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́)
آية رقم 4
tàbí kí ó gbọ́ ìrántí, kí ìrántí náà sì ṣe é ní àǹfààní?
آية رقم 5
Ní ti ẹni tí ó ka ara rẹ̀ kún ọlọ́rọ̀,
آية رقم 7
Kò sì sí ẹ̀ṣẹ̀ fún ọ bí kò bá ṣe àfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́).
آية رقم 8
Ní ti ẹni tí ó sì wá bá ọ, t’ó ń yára gágá (sí ìrántí, ìyẹn afọ́jú),
آية رقم 9
tí ó sì ń páyà (Allāhu),
آية رقم 11
Rárá (kò tọ́ bẹ́ẹ̀). Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
آية رقم 12
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó rántí rẹ̀.
آية رقم 13
(Al-Ƙur’ān) wà nínú àwọn tàkádà alápọ̀n-ọ́nlé,
آية رقم 14
A gbé e ga, A sì ṣe é ní mímọ́
آية رقم 15
ní ọwọ́ àwọn òǹkọtíà (ìyẹn, àwọn mọlāika),
آية رقم 16
àwọn alápọ̀n-ọ́nlé, àwọn ẹni rere.
آية رقم 17
Wọ́n ti fi ènìyàn gégùn-ún (nípa) bí ó ṣe jẹ́ aláìmoore jùlọ!
آية رقم 19
Nínú àtọ̀ l’Ó ti ṣẹ̀dá rẹ̀. Ó sì pèbùbù (ẹ̀yà-ara) rẹ̀.
آية رقم 20
Lẹ́yìn náà, Ó ṣe ọ̀nà àtiwáyé ní ìrọ̀rùn fún un.
آية رقم 21
Lẹ́yìn náà, Ó máa pa á. Ó sì máa fi sínú sàréè.
آية رقم 22
Lẹ́yìn náà, nígbà tí Allāhu bá fẹ́, Ó máa gbé e dìde.
آية رقم 23
Ẹ gbọ́, ènìyàn kò tí ì ṣe n̄ǹkan tí Allāhu pa láṣẹ fún un.
آية رقم 24
Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí oúnjẹ rẹ̀.
آية رقم 25
Dájúdájú Àwa ń rọ òjò ní púpọ̀.
آية رقم 26
Lẹ́yìn náà, A mú ilẹ̀ sán kànkàn.
آية رقم 27
A sì mú kóró èso hù jáde láti inú rẹ̀;
آية رقم 28
àti èso àjàrà àti kànnáfùrù,
آية رقم 29
àti igi òróró Zaetūn àti dàbínù,
آية رقم 30
àti àwọn ọgbà t’ó kún fún igi,
آية رقم 31
àti àwọn èso (mìíràn) pẹ̀lú ewé tí ẹranko ń jẹ, (A mú wọn hù jáde).
آية رقم 32
(Wọ́n jẹ́ n̄ǹkan) ìgbádùn fún ẹ̀yin àti àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
آية رقم 33
Nígbà tí fífọn sínú ìwo nígbà kejì bá ṣẹlẹ̀,
آية رقم 34
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò sá fún arákùnrin rẹ̀,
آية رقم 35
àti ìyá rẹ̀ pẹ̀lú bàbá rẹ̀,
آية رقم 36
àti ìyàwó rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀.
آية رقم 37
Ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn ní ọjọ́ yẹn l’ó ti ní ọ̀ràn t’ó máa tó o ó rán.
آية رقم 38
Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn yóò mọ́lẹ̀.
آية رقم 39
Wọn yó máa rẹ́rìn-ín, wọn yó sì máa dunnú.
آية رقم 40
Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn ni eruku yó sì bò mọ́lẹ̀.
آية رقم 41
Òkùnkùn yó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀.
آية رقم 42
Àwọn wọ̀nyẹn, àwọn ni aláìgbàgbọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.
تقدم القراءة