ترجمة معاني سورة التكوير باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
آية رقم 1
ﭙﭚﭛ
ﭜ
Nígbà tí Wọ́n bá ká òòrùn kóróbójó dànù,
آية رقم 2
ﭝﭞﭟ
ﭠ
àti nígbà tí àwọn ìràwọ̀ bá já bọ́ káàkiri,
آية رقم 3
ﭡﭢﭣ
ﭤ
àti nígbà tí Wọ́n bá mú àwọn àpáta rìn (kúrò ní àyè wọn, tí wọ́n kù wọ́n dànù),
آية رقم 4
ﭥﭦﭧ
ﭨ
àti nígbà tí wọ́n bá pa àwọn ràkúnmí aboyún tì,
آية رقم 5
ﭩﭪﭫ
ﭬ
àti nígbà tí Wọ́n bá ko àwọn ẹranko jọ,
آية رقم 6
ﭭﭮﭯ
ﭰ
àti nígbà tí Wọ́n bá mú àwọn agbami odò gbiná,
آية رقم 7
ﭱﭲﭳ
ﭴ
àti nígbà tí Wọ́n bá so àwọn ẹ̀mí pọ̀ mọ́ra wọn, (ẹni rere pẹ̀lú ẹni rere, ẹni ibi pẹ̀lú ẹni ibi)
آية رقم 8
ﭵﭶﭷ
ﭸ
àti nígbà tí ọmọbìnrin tí wọ́n bò mọ́lẹ̀ láàyè bá bèèrè pé
آية رقم 9
ﭹﭺﭻ
ﭼ
ẹ̀ṣẹ̀ wo ni wọ́n pa òun fún,
آية رقم 10
ﭽﭾﭿ
ﮀ
àti nígbà tí Wọ́n bá ṣí àwọn tákàdá (iṣẹ́ ẹ̀dá) sílẹ̀,
آية رقم 11
ﮁﮂﮃ
ﮄ
àti nígbà tí Wọ́n bá ká sánmọ̀ kúrò lókè,
آية رقم 12
ﮅﮆﮇ
ﮈ
àti nígbà tí wọ́n bá mú iná Jẹhīm jò fòfò,
آية رقم 13
ﮉﮊﮋ
ﮌ
àti nígbà tí Wọ́n bá sún Ọgbà Ìdẹ̀ra mọ́ (àwọn onígbàgbọ́ òdodo),
آية رقم 14
ﮍﮎﮏﮐ
ﮑ
(nígbà náà ni) ẹ̀mí (kọ̀ọ̀kan) yóò mọ ohun tí ó mú wá (nínú iṣẹ́ ire àti iṣẹ́ ibi).
آية رقم 15
ﮒﮓﮔ
ﮕ
Nítorí náà, Èmi (Allāhu) ń búra pẹ̀lú àwọn ìràwọ̀ t’ó ń yọ ní alẹ́, t’ó ń wọ̀ọ̀kùn ní ọ̀sán,
آية رقم 16
ﮖﮗ
ﮘ
(ìyẹn) àwọn ìràwọ̀ t’ó ń rìn lọ rìn bọ̀, t’ó ń wọ̀ọ̀kùn sí ibùwọ̀ wọn.
آية رقم 17
ﮙﮚﮛ
ﮜ
Mo tún búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí ó bá lọ.
آية رقم 18
ﮝﮞﮟ
ﮠ
Mo tún búra pẹ̀lú òwúrọ̀ nígbà tí ó bá mọ́lẹ̀.
آية رقم 19
ﮡﮢﮣﮤ
ﮥ
Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni ọ̀rọ̀ (tí A fi rán Jibrīl) Òjíṣẹ́, alápọ̀n-ọ́nlé,
Wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Hāƙƙọh; 69:40.
آية رقم 20
ﮦﮧﮨﮩﮪﮫ
ﮬ
alágbára, ẹni pàtàkì ní ọ̀dọ̀ Ẹni t’Ó ni Ìtẹ́-ọlá,
آية رقم 21
ﮭﮮﮯ
ﮰ
ẹni tí wọ́n ń tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ níbẹ̀ yẹn (nínú sánmọ̀), olùfọkàntán.
آية رقم 22
ﮱﯓﯔ
ﯕ
Àti pé ẹni yín (Ànábì Muhammad s.a.w.) kì í ṣe wèrè.
آية رقم 23
ﯖﯗﯘﯙ
ﯚ
Ó kúkú rí i nínú òfurufú kedere.
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah an-Najm; 53:13.
آية رقم 24
ﯛﯜﯝﯞﯟ
ﯠ
Àti pé kì í ṣe ahun (tàbí ẹni-afurasí) lórí ìró ìkọ̀kọ̀ (tí A fi ránṣẹ́ sí i).
آية رقم 25
ﯡﯢﯣﯤﯥ
ﯦ
Al-Ƙur’ān kì í sì ṣe ọ̀rọ̀ (tí A fi rán) Èṣù, ẹni ẹ̀kọ̀.
آية رقم 26
ﯧﯨ
ﯩ
Nítorí náà, ibo l’ẹ̀ ń lọ?
آية رقم 27
ﯪﯫﯬﯭﯮ
ﯯ
Kí sì ni al-Ƙur’ān bí kò ṣe ìrántí fún gbogbo ẹ̀dá.
آية رقم 28
ﯰﯱﯲﯳﯴ
ﯵ
(Ó wà) fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti dúró déédé.
آية رقم 29
Ẹ̀yin kò sì níí fẹ́ (láti dúró déédé) àyàfi tí Allāhu bá fẹ́, Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
تقدم القراءة