ترجمة معاني سورة القارعة باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
آية رقم 1
ﭴ
ﭵ
Àkókò ìjáyà.
آية رقم 2
ﭶﭷ
ﭸ
Kí ni Àkókò ìjáyà?
آية رقم 3
ﭹﭺﭻﭼ
ﭽ
Kí sì l’ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Àkókò ìjáyà?
آية رقم 4
ﭾﭿﮀﮁﮂ
ﮃ
(Òhun ni) ọjọ́ tí ènìyàn yó dà bí àfòpiná tí wọ́n fọ́nká síta,
آية رقم 5
ﮄﮅﮆﮇ
ﮈ
àwọn àpáta yó sì dà bí òwú tí wọ́n gbọ̀n dànù.
آية رقم 6
ﮉﮊﮋﮌ
ﮍ
Nítorí náà, ní ti ẹni tí òṣùwọ̀n (iṣẹ́ rere) rẹ̀ bá tẹ̀ wọ̀n,
آية رقم 7
ﮎﮏﮐﮑ
ﮒ
ó sì máa wà nínú ìṣẹ̀mí t’ó yọ́nú sí.
آية رقم 8
ﮓﮔﮕﮖ
ﮗ
Ní ti ẹni tí òṣùwọ̀n (iṣẹ́ rere) rẹ̀ bá sì fúyẹ́,
آية رقم 9
ﮘﮙ
ﮚ
Hāwiyah sì ni ibùgbé rẹ̀.
آية رقم 10
ﮛﮜﮝﮞ
ﮟ
Kí sì ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ bẹ́ẹ̀?
آية رقم 11
ﮠﮡ
ﮢ
(Òhun ni) Iná gbígbóná gan-an.
تقدم القراءة