ترجمة معاني سورة الرحمن باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
آية رقم 1
ﭷ
ﭸ
Àjọkẹ́-ayé,
آية رقم 2
ﭹﭺ
ﭻ
Ó fi ìmọ̀ al-Ƙur’ān mọ (ẹni tí Ó fẹ́).
آية رقم 3
ﭼﭽ
ﭾ
Ó ṣẹ̀dá ènìyàn.
آية رقم 4
ﭿﮀ
ﮁ
Ó sì fi àlàyé (ọ̀rọ̀ sísọ) mọ̀ ọ́n.
آية رقم 5
ﮂﮃﮄ
ﮅ
Òòrùn àti òṣùpá (ń rìn) fún ìṣírò (ọjọ́ ayé).
آية رقم 6
ﮆﮇﮈ
ﮉ
Àwọn ìtàkùn ilẹ̀ àti igi ń forí kanlẹ̀ (fún Allāhu).
آية رقم 7
ﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
Àti sánmọ̀, Allāhu gbé e sókè. Ó sì fi òṣùwọ̀n òfin déédé lélẹ̀ (fún ẹ̀dá)
آية رقم 8
ﮏﮐﮑﮒ
ﮓ
pé kí ẹ má ṣe tayọ ẹnu-àlà níbi òṣùwọ̀n.
آية رقم 9
ﮔﮕﮖﮗﮘﮙ
ﮚ
Ẹ gbé òṣùwọ̀n náà dúró pẹ̀lú dọ́gbadọ́gba. Kí ẹ sì má ṣe dín òṣùwọ̀n kù.
آية رقم 10
ﮛﮜﮝ
ﮞ
Ilẹ̀, (Allāhu) tẹ́ ẹ sílẹ̀ fún àwọn ẹ̀dá.
آية رقم 11
ﮟﮠﮡﮢﮣ
ﮤ
Èso àti dàbínù alápó wà lórí (ilẹ̀).
آية رقم 12
ﮥﮦﮧﮨ
ﮩ
Àti èso kóró onípòpórò àti eléwé dúdú (wà lórí ilẹ̀).
آية رقم 13
ﮪﮫﮬﮭ
ﮮ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 14
ﮯﮰﮱﯓﯔ
ﯕ
(Allāhu) ṣẹ̀dá ènìyàn láti ara amọ̀ gbígbẹ t’ó ń dún kokoko bí ìkòkò amọ̀.
آية رقم 15
ﯖﯗﯘﯙﯚﯛ
ﯜ
Ó sì ṣẹ̀dá àlùjànnú láti ara ahọ́n iná tí kò ní èéfín.
آية رقم 16
ﯝﯞﯟﯠ
ﯡ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 17
ﯢﯣﯤﯥ
ﯦ
Olúwa ibùyọ òòrùn méjèèjì àti ibùwọ̀ òòrùn méjèèjì.
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Mọ‘ārij; 70:40.
آية رقم 18
ﯧﯨﯩﯪ
ﯫ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 19
ﭑﭒﭓ
ﭔ
(Allāhu) mú odò méjì (odò oníyọ̀ àti odò aládùn) ṣàn pàdé ara wọn.
آية رقم 20
ﭕﭖﭗﭘ
ﭙ
Gàgá kan sì wà láààrin àwọn méjèèjì tí wọn kò sì lè tayọ ẹnu-àlà (rẹ̀ láààrin ara wọn).
آية رقم 21
ﭚﭛﭜﭝ
ﭞ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 22
ﭟﭠﭡﭢ
ﭣ
Òkúta oníyebíye àti ìlẹ̀kẹ̀ iyùn ń jáde nínú àwọn (odò) méjèèjì náà.
آية رقم 23
ﭤﭥﭦﭧ
ﭨ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 24
ﭩﭪﭫﭬﭭﭮ
ﭯ
Ti (Allāhu) ni àwọn ọkọ̀ ojú-omi gogoro t’ó ń rìn nínú agbami òdò (tí wọ́n dà) bí àpáta gíga.
آية رقم 25
ﭰﭱﭲﭳ
ﭴ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 26
ﭵﭶﭷﭸ
ﭹ
Gbogbo ẹni t’ó wà lórí ilẹ̀ máa tán.
آية رقم 27
ﭺﭻﭼﭽﭾﭿ
ﮀ
Ojú Olúwa rẹ, Atóbi, Alápọ̀n-ọ́nlé sì máa wà títí láéláé.
آية رقم 28
ﮁﮂﮃﮄ
ﮅ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 29
Àwọn t’ó wà nínú àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀ ń bèèrè (n̄ǹkan) lọ́dọ̀ Rẹ̀; Ó sì wà lórí ìṣe lójoojúmọ́.
آية رقم 30
ﮒﮓﮔﮕ
ﮖ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 31
ﮗﮘﮙﮚ
ﮛ
A óò mú tiyín gbọ́ (lọ́jọ́ ẹ̀san), ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú.
آية رقم 32
ﮜﮝﮞﮟ
ﮠ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 33
Ẹ̀yin àwùjọ àlùjànnú àti ènìyàn, tí ẹ bá lágbára láti sá jáde nínú àwọn agbègbè sánmọ̀ àti ilẹ̀, ẹ sá jáde. Ẹ ò lè sá jáde àfi pẹ̀lú agbára.
آية رقم 34
ﯔﯕﯖﯗ
ﯘ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 35
Wọ́n máa ju ẹ̀ta-pàrà iná àti ẹ̀ta-pàrà idẹ lé ẹ̀yin méjèèjì lórí, ẹ̀yin méjèèjì kò sì lè ran’ra yín lọ́wọ́.
آية رقم 36
ﯢﯣﯤﯥ
ﯦ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 37
ﯧﯨﯩﯪﯫﯬ
ﯭ
Nítorí náà, nígbà tí sánmọ̀ bá fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, ó sì máa pọ́n wá wẹ̀ bí epo pupa.
آية رقم 38
ﯮﯯﯰﯱ
ﯲ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 39
Nítorí náà, ní ọjọ́ yẹn Wọn ò níí bi ènìyàn àti àlùjànnú kan léèrè nípa ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; (ó ti wà ní àkọsílẹ̀ ní ọ̀dọ̀ Wa).
آية رقم 40
ﯼﯽﯾﯿ
ﰀ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 41
ﰁﰂﰃﰄﰅﰆ
ﰇ
Wọ́n máa mọ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú àmì ara wọn. Wọ́n sì máa fi àásó orí àti ẹsẹ̀ gbá wọn mú.
آية رقم 42
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 43
ﭖﭗﭘﭙﭚﭛ
ﭜ
Èyí ni iná Jahanamọ tí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ń pè nírọ́.
آية رقم 44
ﭝﭞﭟﭠﭡ
ﭢ
Wọn yóò máa rìn lọ rìn bọ̀ láààrin Iná àti omi t’ó gbóná parí.
Ìyẹn ni pé, nínú Iná, yàtọ̀ sí pé oríṣiríṣi omi burúkú l’ó wà nínú rẹ̀ bíi omi t’ó gbóná parí, omi rẹ́funrẹ́fun, omi ètútú, omi àwọnúwẹ̀jẹ̀, àwọn omi wọ̀nyí máa wà nínú ọ̀gbun kan fún àwọn ọmọ Iná nínú Iná, bí Iná bá ti ń jó wọn, bẹ́ẹ̀ náà ni wọ́n á lọ máa mu omi ìmukúmu wọ̀nyí sí i, wọ́n á tún padà síbi Iná, wọ́n á tún padà síbi omi, wọ́n á tún padà síbi Ina. Wọ́n á wà bẹ́ẹ̀ títí láéláé.
آية رقم 45
ﭣﭤﭥﭦ
ﭧ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 46
ﭨﭩﭪﭫﭬ
ﭭ
Ọgbà Ìdẹ̀ra méjì ń bẹ fún ẹni t’ó bá páyà ìdúró rẹ̀ níwájú Olúwa rẹ̀.
آية رقم 47
ﭮﭯﭰﭱ
ﭲ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 48
ﭳﭴ
ﭵ
(Àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra méjèèjì ní) àwọn ẹ̀ka igi gígùn.
آية رقم 49
ﭶﭷﭸﭹ
ﭺ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 50
ﭻﭼﭽ
ﭾ
Odò méjì t’ó ń ṣàn wà nínú ọgbà méjèèjì.
آية رقم 51
ﭿﮀﮁﮂ
ﮃ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 52
ﮄﮅﮆﮇﮈ
ﮉ
Oríṣi méjì méjì ni èso kọ̀ọ̀kan t’ó wà nínú ọgbà méjèèjì.
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah Yāsīn; 36:36.
آية رقم 53
ﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 54
Wọn yóò rọ̀gbọ̀kú lórí ìtẹ́, tí àwọn ìtẹ́ inú rẹ̀ jẹ́ àrán t’ó nípọn. Àwọn èso ọgbà méjèèjì sì wà ní àrọ́wọ́tó.
آية رقم 55
ﮚﮛﮜﮝ
ﮞ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 56
Àwọn obìnrin tí kì í wo ọkùnrin mìíràn wà nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra. Ènìyàn àti àlùjànnú kan kò sì fọwọ́ kàn wọ́n rí ṣíwájú wọn.
آية رقم 57
ﮩﮪﮫﮬ
ﮭ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 58
ﮮﮯﮰ
ﮱ
Wọ́n dà bíi ìlẹ̀kẹ̀ ṣẹ̀gi àti ìlẹ̀kẹ̀ iyùn.
آية رقم 59
ﯓﯔﯕﯖ
ﯗ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 60
ﯘﯙﯚﯛﯜ
ﯝ
Ǹjẹ́ ẹ̀san mìíràn wà fún ṣíṣe rere bí kò ṣe (ẹ̀san) rere.
آية رقم 61
ﯞﯟﯠﯡ
ﯢ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 62
ﯣﯤﯥ
ﯦ
Ọgbà méjì kan tún ń bẹ yàtọ̀ sí méjì (àkọ́kọ́ yẹn).
آية رقم 63
ﯧﯨﯩﯪ
ﯫ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 64
ﯬ
ﯭ
Aláwọ̀ ewéko (ni Ọgbà méjèèjì náà).
آية رقم 65
ﯮﯯﯰﯱ
ﯲ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 66
ﯳﯴﯵ
ﯶ
Àwọn odò méjì t’ó ń tú omi jáde láì dáwọ́ dúró wà (nínú ọgbà méjèèjì náà).
آية رقم 67
ﯷﯸﯹﯺ
ﯻ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 68
ﯼﯽﯾﯿ
ﰀ
Èso ìpanu, dàbínù àti èso rumọ̄n wà nínú ọgbà méjèèjì.
آية رقم 69
ﰁﰂﰃﰄ
ﰅ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 70
ﭑﭒﭓ
ﭔ
Àwọn obìnrin rere, arẹwà wà nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra.
آية رقم 71
ﭕﭖﭗﭘ
ﭙ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 72
ﭚﭛﭜﭝ
ﭞ
Àwọn ẹlẹ́yinjú-ẹgẹ́ kan (ni wọ́n), tí A fi pamọ́ sínú ilé-ọ̀ṣọ́.
آية رقم 73
ﭟﭠﭡﭢ
ﭣ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 74
ﭤﭥﭦﭧﭨﭩ
ﭪ
Ènìyàn àti àlùjànnú kan kò fọwọ́ kàn wọ́n rí ṣíwájú wọn.
آية رقم 75
ﭫﭬﭭﭮ
ﭯ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 76
ﭰﭱﭲﭳﭴﭵ
ﭶ
Wọn yóò rọ̀gbọ̀kú lórí àwọn tìmùtìmù aláwọ̀ ewéko àti ìtẹ́ t’ó dára.
آية رقم 77
ﭷﭸﭹﭺ
ﭻ
Nítorí náà, èwo nínú àwọn ìdẹ̀ra Olúwa ẹ̀yin ènìyàn àti àlùjànnú ni ẹ máa pè nírọ́?
آية رقم 78
ﭼﭽﭾﭿﮀﮁ
ﮂ
Ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi, Alápọ̀n-ọ́nlé.
تقدم القراءة